You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Robbery notification: Ẹ wo ọ̀nà àbáyọ tí adigunjalè bá kọ lẹ́tà sí yín pé àwọn fẹ́ ẹ́ wá jà yín lólè
Onimọ kan nipa eto aabo, Ọgbẹni Akin Adeyi ti sọrọ lori nkan ti awọn araalu le ṣe nigbakuugba ti wọn ba gba lẹta ẹru lọwọ adigunjale.
Nigba ti BBC ba sọrọ lori iroyin to n lọ nipa awọn adigunjale kan to kọ lẹta si adugbo Olopa Estate, Ofatede, nijọba ibilẹ Egbedore, nipinlẹ Osun, Ọgbẹni Adeyi sọ pe nkan akọkọ fun iru adugbo bẹẹ lati sẹ ni pe ki wọn o bẹrẹ si ni fi oju silẹ lati ri awọn nkan to yẹ.
- Ọmọ ọdún méje ni mo ti ń digunjalè, ogun ìdílé ló fàá, afurasí ṣàlàyé l'Ondo
- Wo iléẹ̀kọ́ tí wọ́n kò ti fààyè gba akẹ́kọ̀ọ́ láti padà sọ́dọ̀ Òbí tàbí ìlú rẹ̀ lẹ́yìn tó bá parí
- Alàgbà Gumi, ẹ lọ mèṣọ́nu lórí àwọn ọ̀rọ̀ tó lè máa ki àwọn agbébọn láyà- Iléeṣẹ́ Ológun Nàìjíríà
- Gọngọ́ sọ, àwọn Ṣọ́jà lé ọlọ́pàá lùgbẹ́ lágọ́ ọlọ́pàá l' Osogbo
- Ọmọ ọdún méje ni mo ti ń digunjalè, ogun ìdílé ló fàá, afurasí ṣàlàyé l'Ondo
"O yẹ ki awọn ara adugbo naa yẹ ara wọn wo, lati mọ awọn eeyan buruku to n gbabọde laarin wọn."
O ni o sẹ pataki fun awọn to ba n gbe niru adugbo bẹẹ, lati ma ṣe akiyesi irinsi gbogbo eeyan ni adugbo wọn, paapaa awọn to ba jẹ ajeeji tabi ti iṣesi wọn mu ifura dani.
Bakan naa lo sọ pe ki awọn ara adugbo fi nkan ifura ti wọn ba ri to ileeṣẹ ọlọpaa leti ni kiakia, nitori pe imọ ti awọn ọlọpaa ba ni, ni wọn o fi pese abo.
Akin Adeyi ni: "Gbigbe igbesẹ oju ni alakan fi n sọri ni ọna abayọ to le dena iru awọn nkan bayii."
O ṣalaye pe gẹgẹ bi olugbe nilu Osogbo, oun le fidirẹ mulẹ pe kii ṣe igba akọkọ niyii ti adigunjale kọ lẹta si adugbo naa.
O ni ṣugbọn iyatọ to wa ninu lẹta ti wọn kọ lọtẹ yii ni bi wọn ṣe ni ki wọn o ko owo itanran fun alaga ẹgbẹ awọn larinlọọdu ni adugbo naa.
O tẹsiwaju pe iwadii yẹ ko waye lori aṣẹ naa, botilẹ jẹ pe ẹnikẹni ko ti i le sọ boya alaga naa mọ tabi lọwọ si iṣẹ awọn adigunjale naa.
Àwọn adigunjalè kọ lẹ́tà sí adúgbò, wọ́n ni kí ara àdúgbò dá 20m tàbí kí wọ́n ó jàwọ́n lólè
Ibẹru -bojo lo gbalẹ laarin awọn olugbe agbegbe Olopa Estate, Ofatede, nijọba ibilẹ Egbedore, nipinlẹ Osun, lẹyin ti awọn adigunjale kọwe ranṣẹ si wọn pe awọn yoo ja wọn lole.
Lẹta naa, ti wọn kọ ni ede oyinbo ati Yoruba, ni wọn ti paṣẹ fun awsn to n gbe ni agbegbe naa pe ki wọn o da ogun miliọnu Naira jọ , lati dena ki awọn ma ba a ja wọn lole.
Yatọ si eyi, awọn adigunjale naa sọ pe ọwọ alaga ẹgbẹ awọn olugbe ni adugbo naa ni ki wọn o tọju owo naa si, ko le rọrun lati gba nigba ti awọn ba de.
- Àwọn adigunjalè pa èèyàn bí mẹ́rin, níbi ìkọlu bánkì méjì ni Ikire àti Apomu
- Arákùnrin ọlọ́kadà kan àti bàbá ágbalagbà kan làwọn adigunjalè pa l'Okuku --Ọlọ́pàá
- Wo ikọ̀ aláàbò tuntun tí yóò gba iṣẹ́ ọlọ́pàá SARS ṣe l'Eko
- Wo iléẹ̀kọ́ tí wọ́n kò ti fààyè gba akẹ́kọ̀ọ́ láti padà sọ́dọ̀ Òbí tàbí ìlú rẹ̀ lẹ́yìn tó bá parí
- Ọmọ ọdún méje ni mo ti ń digunjalè, ogun ìdílé ló fàá, afurasí ṣàlàyé l'Ondo
- Èèyàn kan ti kú, 99 di àwátì lẹ́yìn tí ilé alájà méjìlá wó lulẹ̀ l'óru
Wọn ni "eyi ni lati sọ fun yin pe , awa ole n bọ wa a ja gbogbo ile to wa ni adugbo yin lole, tabi ki ẹ da ogun miliọnu Naira jọ , ki ẹ si tọju rẹ si ọdọ alaga yin, ka le gba a nibẹ ti a ba de.
"Pẹlu agbara ni a n bọ, ao si pa eyikeyi oṣiṣẹ alaabo yin to ba gbiyanju lati di wa lọwọ."
Ẹnikan to n gbe ni adugbo naa to ba awọn akọroyin sọrọ sọ pe lati igba ti wọn ti kọ lẹta naa ni awọn eeyan kan ko ti sun ile wọn mọ, to si jẹ pe ọsan ni wọn ma n wa si ile lati ko awọn nkan ti wọn ba nilo.
Ati pe awọn ọlọdẹ to jẹ oṣiṣẹ alaabo ti pọ si ni adugbo naa.
- Mó ṣèlérí láti buwọ́lu àtúntò Naijiria, Ilé Aṣòfin o kù sí ọwọ́ yín - Ààrẹ́ Buhari
- Èèyàn kan ti kú, 99 di àwátì lẹ́yìn tí ilé alájà méjìlá wó lulẹ̀ l'óru
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń ṣelédè lẹ́yìn Ajimobi, èrò wọn ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀!
- Àwọn lọ́balọ́ba nílẹ̀ Yoruba dalẹ̀ wa lórí àwọn ọmọ OPC mẹ́ta tí wọ́n tímólé láìṣẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ Iskilu Wakili - Ẹgbẹ́ OPC
- Wo àwọn ìlànà tí ó máa tẹ̀lé láti wo èsì ìdánwò 2021 Jamb UTME rẹ lórí ayélujára àti SMS