You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Bí ó bá ṣè ẹbọ ló gbà, ẹ fín-in kí àlááfíà lè j'ọba ní Oyo- Makinde sọ f'áwọn ẹlẹ́sìn àbáláyé
Ijọba ipinlẹ Ọyọ ati apapọ ẹgbẹ awọn ẹlẹsin abalaye nipinlẹ naa ti fohunṣọkan lati ṣe amulo agbara iṣẹmbaye lojuna ati fopin si iṣoro eto aabo.Igbesẹ naa jẹ ọkan lara awọn abajade apẹro lori eto aabo ati ibaraẹni gbe ninu alafia to waye l'Ọjọru ni ẹka ileeṣẹ iroyin, aṣa ati irinajo igbafẹ nilu Ibadan.
Kọmisana fun iroyin, aṣa ati irinajo igbafẹ Ọmọwe Wasiu Ọlatunbọsun lo ṣe agbekale ipade naa lorukọ ijọba ipinlẹ Ọyọ.
Olatunbosun fi ayọ ijọba han lori atilẹyin ti awọn ẹlẹsin abalaye n ṣe fun Gomina ipinlẹ Ọyọ lati igba ti o ti gun ori aleefa.
Ọlatunbọsun kede rẹ pe ijọba Ṣeyi Makinde ti gbe igbesẹ lati fun awọn ẹlẹsin abalaye ni ọjọ ti wọn a maa gba isinmi lẹnu iṣẹ gẹgẹ bi awọn ẹlẹsin to ku lati ṣe ọdun wọn.
O ni ilana ofin ati awọn igbesẹ kọọkan lo n ṣe idaduro fun ikede ọjọ naa.
- Kàyèéfì! Wo ìdí tí àlùfáà ìjọ Aguda fi ń kó ère ìṣẹ̀nbáyé pamọ́?
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Babaláwo rí ẹ̀wọ̀n he! lẹ́yìn tó ṣe ìwòsàn fún obìnrin pẹ̀lu tábà fínfín, ló bá kú lójijì!
- Wo ìlú márùn-ún tó ń bọ tàbí sin ejò bí ọlọ́run, ṣé ìlú rẹ̀ wà lára wọn tí o kò mọ̀?
- Ṣé lóòtọ́ ni olè kan wọlè fipá bá ìyá 80 lòpọ̀ nípìnlẹ̀ Ondo?
- Buhari ní kí ilé aṣòfin àgbà buwọ́lu N895b gẹ́gẹ́ bíi àfikún owó ètò ìṣúná ọdún 2021
Kọmisana naa kesi awọn ẹlẹsin abalaye naa lati sa gbogbo ipa wọn tofimọ ẹbọ riru ki alafia le jọba nipinlẹ Ọyọ.
O fi kun ọrọ rẹ wi pe "a ni lati pada si ilana ti awọn babanla wa fi n yanju iṣoro eto aabo nigba iwasẹ, ki ipinlẹ Ọyọ le tuba ki o si tuṣẹ".
Oluranlọwọ pataki fun Gomina Ṣeyi Makinde lori iṣakoso, Ẹniọwọ Idowu Ogedengbe to ba wọn pejupesẹ sibi ipade naa kesi awọn ẹlẹsin abalaye lati tẹsiwaju ninu ṣiṣe atilẹyin fun ijọba to n bẹ lode ki iṣẹ idagbasoke le tẹsiwaju.
- Ọ̀rọ̀ agọ̀ ni Dambazau sọ bó ṣe fi OPC wé Boko Haram - Àgbààgbà Yorùbá
- Ìyàwó Ooni Ogunwusi, Olori Naomi Silekunola lọ ibi ìsọmọlórúkọ Kemisola, ayé gbọ́!
- Yinka Alaṣeyori fi ọ̀rọ̀ ìjínlẹ̀ púpọ̀ àti omijé ṣàlàyé Oniduro Mi
- Ẹranko àìmọ́ kan wọ Nàìjíríà, ó pa ènìyàn mẹ́rin ní Benue- ilé iṣẹ́ ọmọogun ni ìròyìn òfegè ni
- Ẹ̀wọ̀n ọdún méje gbáko ni adájọ́ sọ pé kí Farouk Lawan fi ṣara ridin!
- Ẹ̀bùn owó, oúnjẹ, aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ ní ìkókó mú wọlè fún ẹbí Kemisola Ogunniyi ní Ondo
Aare Isẹṣẹ ipinlẹ Ọyọ, Aare Omikunmi Egbelade, Alaga Aṣa Oriṣa ilẹ Naijiria, Oloye Oke Adejare ati Oba Ela ipinlẹ Ọyọ, Oba Ojebode Awoniran ke si ijọba lati gbe owo kalẹ fun awọn ẹlẹsin mẹta gboogi to n bẹ nipinlẹ Ọyọ fun akanṣe eto adura ati irubọ.
Ẹwẹ, bakan naa ni ijọba ṣe ipade pẹlu awọn aṣoju eleegun lori ibara ẹni gbe ninu alaafia ti ijọba Gomina Ṣeyi Makinde n fọn rere rẹ.