Bandits Attacks: Àwọn aṣòfin àpapọ̀ fọnmú pé ọwọ́ àwọn ológun kò mọ́ lórí ìkọlù agbébọn

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn aṣofin apapọ Naijiria ti beere fun yiyọ olubadamọran abo fun aarẹ Naijiria, Ọgagunfẹ̀yinti Babagana Monguno ati minisita feto abo, ọgagunfẹyinti Bashir Magashi kuro nipo wọn.
Awọn aṣofin ile aṣoju-ṣofin Naijiria tun fẹsun kan awọn agbofinro pe awọn gan n ṣe agbodegba fawọn agbebọn ati awọn ọdaran to n da Naijiria laamu.
Ile asofin apapọ ni awọn agbofinro yii ni ko si jẹ ki gbogbo obitibiti owo ti wọn n ya sọtọ fun kikọju ogun si aabo to mẹhẹ yọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣe lóòótọ́ ni pé Osinbajo kìí se ọmọ ẹgbẹ́ APC l‘Eko?
- Ìdí tí Tinubu fi ṣèpàdé pẹ̀láwọn gómìnà APC lẹ́yìn tí Osinbajo kéde lati dupò ààrẹ
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní pé Osinbajo dalẹ̀ Tinubu pẹ̀lú bó ṣe kéde láti du ipò ààrẹ?
- Ìkọlù sí Ukraine kò ní dópin àyàfi tó bá ṣe ohun tí mo fẹ́ - Putin
- Tí mo bá di ààrẹ, ìwúrí ni màá jẹ́ fọ́mọ Nàíjíríà - Tunde Bakare
- Mo fẹ́ pokùnso torí ìjákulẹ̀ tí ọ̀gá mi, Yekini Ajileye fún mi, ọpẹ́ tọ́ọ́gì kan... - Abija
- Erin kọlu Amaya Sebastian, àgbà ọ̀jẹ́ ọjọ́gbọ́n nínú isẹ́ ìwádìí kan, ikú ló padà já sí
- Àjọ INEC ní àwọn káàdì ìdìbò kan kò wúlò mọ́ láti fi dìbò lọ́dún 2023
- Ìwúlò Buhari fún Nàíjíríà tí tán, kò búrú tó bá kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ - Ilana Omo Oodua
- Ó ti tán fún Nàìjíríà bí ará Àríwá bá tún di Ààrẹ lọ́dún 2023 - Adebanjo
- Nǹkan márùn-ún tó yẹ kí o mọ̀ nípa Peter, ọkọ Osinachi, tí wọ́n fi ẹ̀sùn ikú aya rẹ̀ kàn
- Ẹ dákun, ẹ gbà mí, Auxillary ń lépa ẹ̀mí mi - Olopoeyan kọ̀wé sí ọlọ́pàá, DSS
Bakan naa ni wọn tun fi ẹsun kan awọn adari ẹka ileeṣẹ abo ati agbofinro gbogbo lorilẹede naa pe awọn pẹlu n jifa ninu bi rọ abo ṣe mẹhẹ nitori owo gọbọi ti wọn n ya sọtọ fun ẹka naa.
"Ṣe aarẹ ko wa mọ pe nnkan o lọdaadaa fun awọn eeyan orilẹede yii ni?"
Ni ọjọ Aiku nikan, ko din ni aadọrin eeyan tawọn agbebọn yinbọn pa lawọn ileto kan nijọba ibilẹ Kanam ati Wase nipinlẹ Plateau
Ni ọjọ Aje rẹ, eeyan marundinlọgbọn miran ni wọn tun pa nijọba ibilẹ Guma ati Tiortyu nipinlẹ̀ Benue.
Awọn iku ọwọọwọ yii lo mu ki alaga igbimọ̀ tẹẹkoto lori ọrọ ileeṣẹ ọmọogun oju omi, iyẹn Họnọrebu Yusuf Gagdi fi gbe aba kan dide lori awọn isẹlẹ aabo to mẹhẹ yii.
Lati ipasẹ aba naa lo ti jẹ ki gbogbo ile mọ pe ko si eredi fun ijọba ti ko ba mọ ipese abo to peye ati igbayegbadun araalu jẹ ara koko kan gboogi idi ti oun fi wa nipo.
O ni o ṣe ni laanu pe ni Naijiria tawọn agbebọn ti n pa araalu nipakupa yii, "a ni aarẹ. A ni gomina pẹlu.
A ni ile igbimọ aṣofin apapọ, a ni sẹnetọ atawọn aṣojuṣofin gbogbo. Ta gan lo wa ni akoso alaafia ati igbayegbadun ati abo araalu lorilẹede yii? Laini deena pẹnu gbogbo wa la mọ pe aarẹ ni.
"Ṣe aarẹ ko wa mọ pe nnkan o lọ daadaa fun awọn eeyan orilẹede yii ni? Ṣe o n gun gbogbo awọn adari ikọ alaabo gbogbo tọrọ kan pẹlu aisi abo yii ni kẹsẹ?"

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn ọmọogun lo n fun awọn agbebọn ni aṣọ iṣẹ wọn lati ṣọṣẹ ni Plateau -Igbakeji olori ile
Igbakeji olori ile aṣoju-ṣofin, Họnọrebu Ahmed Wase, to ṣakoso ijoko ile lọjọru fi ẹsun kan pe ileeṣẹ̀ agbofinro gbogbo lo n ṣe agbodegba fawọn agbebọn ati ọdaran gbogbo lorilẹede Naijiria.
Họnọrebu Wase, ti ilu rẹ wa lara awọn agbegbe tawọn agbebọn naa kọlu, ni iye awọn eeyan ti wọn n gbe kiri pe awọn agbebọn naa pa kere si iye awọn eeyan ti wọn pa lọ.
O ni nitori eto isinku alapapọ lawọn eeyan agbegbe naa n ṣe fun ọgọrọ eeyan tawọn agbebọn naa pa nibẹ.
"Ni ileto temi, a ni ṣọja kan to yẹ ko wa ni Zamfara, ti wọn si n fun laaye isinmi ni ṣisẹ n tẹle fun oṣu mẹfa.
Ọwọ tẹ ẹ pe o n fun awọn agbebọn ni aṣọ iṣẹ ologun rẹ, titi di bi mo ṣe n sọrọ yii, ko tii fi oju wina ofin o.
Bi o ba yẹ ko wa lẹnu iṣẹ ni Zamfara, ti ọwọ si wa tẹ ẹ ni Plateau, ta lo n fun un laaye lati kuro loju iṣẹ?
Ki si ni idi ti wọn fi n fun ologun to yẹ ko wa loju ija ni iyọnda oṣu mẹfa?
BBC Yoruba kan si agbẹnusọ fun ileesẹ ologun lati mọ iha wọn si awọn sun naa amọ o ni oun yoo kan si wa [pada laipẹ lẹyin ti oun ba gbọ ẹkunrẹrẹ ijiroro awọn asofin naa.

















