RCCG Directorate of Politics: Ìjọ RCCG fèsì sí awuyewuye pé torí Osinbajo ni ẹ̀ka òṣèlú ṣe wà ní ìjọ náà

Oríṣun àwòrán, RCCG
Ijọ Redeemed Christian Church of God eyi ti Pasitọ Enoch Adeboye n dari ti sọrọ sita lori iroyin to jade pe wọn da ẹka eto oṣelu kalẹ ninu ijọ naa.
Lori igbesẹ yii, kete ti awọn eniyan rii ni awuyewuye ti n lọ lode pe nitori Pasitọ to tun jẹ ọmọ ijọ naa to jẹ igbakeji aarẹ Naijiria, Adajọ agba, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo ni wọn ṣe ṣe e.
"Haaa, tori erongba Yemi Osinbajo lati dije dupo aarẹ Naijria lọdun 2023 ni ijọ RCCG ṣe da a bi ọgbọn". Eyi ni ọrọ to n jade lẹnu awọn mii.
Bakan naa ni awọn mii n sọ pe ohun to dara ju ni ijọ RCCG ṣe yii toripe kii ṣe Osinbajo nikan ni ọmọ ijọ RCCG to wa ninu oṣelu o si yẹ ko jẹ ọna lati maa ṣọ iṣe wọn ni ipo ti wọn ba wa.
Nitori naa, ijọ naa ti sọ pe irọ ni o, kii sii ṣe tori igbakeji aarẹ Osinbajo tabi tori ẹnikẹni to ba ni erongba oṣelu lọdun 2023 ni awọn ṣe gbe ẹka tuntun naa kalẹ.
Adari ẹka iroyin ati ọrọ to kan araalu, Pasitọ Olaitan Olubiyi sọ eyi ninu esi rẹ si ibeere ileeṣẹ iroyin Punch.
Gẹgẹ bo ṣe ṣalaye, ẹka ọrọ oṣelu ijọ naa jẹ eyi ti wọn da silẹ lati ṣe ilanilọyẹ fawọn ọmọ ijọ ki wọn kopa gidi ninu oṣelu to fi mọ ki wọn gba kaadi idibo alalopẹ wọn ṣaaju idibo gbogboogbo ti ọdun 2023.
Bakan naa ni Olubiyi sọ pe ijọ RCCG ti n ṣe ilanilọyẹ nipa oṣelu fawọn ọmọ ijọ rẹ lati igba ti ijọba ologun ti gbe ijọba fun alagbada latọdun 1999 ko si si tuntun tabi babara ninu igbesẹ naa.
O ni awọn Kristẹni ko le tẹsiwaju láti maa jẹ ki wọn gbe wọn mọra nipa yiyọwọ kuro ninu oṣelu nitori gbogbo eeyan ipinu yiyan adari ninu oṣelu yoo ni ipa lara rẹ.
Agbẹnusọ ijọ RCCG yii wa tubọ gba awọn ijọ to ku ni Naijiria ati ibi gbogbo ni imọran pe ki wọn fi ohun ti awọn ṣe yii ṣe awokọṣe nipa ṣiṣe ilanlọyẹ fawọn ọmọ ijọ wọn ki wọn maa kopa ninu oṣelu.
Ninu atẹjade kan ti igbakeji oludari ijọ RCCG, Pasitọ John Odesola fọwọ si eyi ti wọn fi ranṣẹ si gbogbo ẹka ijọ RCCG ni wọn ti sọ sinu ẹ pe wọn da ẹka naa silẹ fun idanilẹkọ awọn ọmọ ijọ ni.
"A n beere fun pe ki ẹ yan oludari kan ni ẹkun ti ẹ wa gẹgẹ bi adari kiakia ti yoo maa ṣakoso ati ki ẹ si ṣe bẹẹ ni gbogbo ẹka ijọ. Idi eyi ni lati ṣeranwọ kikọ awọn eeyan wa to nifẹ lati kopa ninu oṣelu ki si ṣeto atilyin fun wọn nigba ti o ba nilo".
Ijọ RCCG ni ijọ to tobi ju lọ ni Naijiria to si ni ẹka ni awọn orilede agbaye to le ni ẹẹdẹgbẹwa. RCCG ni awọn ilumọọka ọmọ ijọ ati Pasitọ ninu ijọba lara wọn si ni igbakeji aarẹ Yemi Osinbajo, iyawo adari ẹgbẹ oṣelu APC, Remi Tinubu ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Bo tilẹ jẹ pe Bola Tinubu ti kede erongba rẹ lati du ipo aarẹ, Yemi Osinbajo ko tii kede erongba tirẹ.
Ẹwẹ, alatilẹyinati ololufẹ rẹ ti n rọ ọ lati kede ko si tẹwọ gba eku ida iṣejọba lọwọ Aarẹ Muhammadu Buhari lọdun 2023.
Ki ni ijọ Redeem Christian Church of God fẹ fi ẹka ọrọ oṣelu to da silẹ ṣe ni ibeere ti ọpọ n beere?
Eyi waye ni kete ti iroyin jade pe ijọ naa ti da ẹka kan silẹ fun ọrọ oṣelu ati iṣejọba ṣaaju eto idibo apapọ Naijiria ti yoo waye lọdun 2023.
Ijọ RCCG kede rẹ ninu iwe kan to kọ si awọn ẹka ati oṣiṣẹ rẹ pe ẹka tuntun yii ni yoo maa dari eto gbogbo nipa awọn ọmọ ijọ naa to ba fẹ dije fun ipo oṣelu lọdun 2023.
- Mo ṣèlérí pé n kò ní já Ibadan àti Nàìjíríà kulẹ̀- Olúbàdàn tuntun, Ọba Lekan Balogun Ali Okùmádé kejì
- Ẹ yé wá ọkùnrin tó lówó kiri láti fẹ́- Charly Boy ṣèkìlọ̀ fún àwọn obìnrin
- Dókítà ní ọdún márùn-ún ló kù fún mi láyé, mo sì ti lò lára rẹ̀ - Òṣèré Kemi Afolabi
- Wọ́n ti gbé dẹ́rẹ́bà ọ̀kọ̀ BRT tí Bamise wọ̀ lọ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Kirikiri
Bakan naa ni ijọ RCCG tun kede orukọ Pasitọ Timothy Ọlaniyan to jẹ oluṣọaguntan fun ẹkun kejila nipinlẹ Eko, Lagos Province 12 gẹgẹ bi adari ẹka naa.
Wọn wa kan sawọn oluṣọaguntan lẹkun, ipinlẹ ati agbegbe gbogbo lati yan awọn eeyan ti yoo mojuto ẹka yii lagbegbe koowa wọn.

Oríṣun àwòrán, other
Ki lo wa ninu iwe naa?
Iwe naa ti akori rẹ jẹ RCCg/AGO/ADM/AA.MEMO/20/01/2022 ti igbakeji pasitọ agba ijọ RCCG, Pasitọ J.F. Ọdẹṣọla buwọlu sọ ọ sinu rẹ pe:
"A n kọ iwe yii lati fi to yin leti pe awọn alaṣẹ iṣẹ iranṣẹ yii ti da ẹka amojuto ọrọ oṣelu ati iṣejọba ninu ijọ RCCG.
Nitori eyi, Pasitọ Timothy Ọlaniyan, alakoso ẹkun ikejila nipinlẹ̀ Eko (lagos Province 12) lati maa ṣe akoso ẹkoso ẹka yii.
A rọ ẹyin naa lti yan awọn eeyan lẹkun yin lati mojuto ẹka yii ki ilana yii lee wa kaakiri gbogbo ẹka ati ẹkun.
Ẹ gbọdọ fi akọsilẹ nipa gbogbo awọn ti ẹ ba yan ranṣẹ si ọfiisi igbakeji alamojuto agba iṣẹ iranṣẹ yii to n mojuto ọrọ iṣakoso."


















