Lagos-Ibadan road accident: Ìjàmbá ọkọ̀ gbẹ̀mí èèyàn mẹ́tàdínlógún lọ́nà Ibadan

Oríṣun àwòrán, @LASEMA
O kere tan, eeyan mẹtadinlogun lo jona raurau ninu ijamba ọkọ to ṣẹlẹ loju popo ilu Eko si Ibadan lọjọ Ẹti.
Ọkọ bọọsi Mazda akero kan ni wọn lo kọlu tanka agbepo lori afara Isara loju popo naa.
Ọga ajọ ẹṣọ oju popo, FRSC, ni ipinlẹ Ogun, Ahmed Umar lo fidi iṣẹlẹ ọhun mulẹ fawọn akọroyin.
- Ìbẹ̀rù-bojo gbalẹ̀ ṣáájú ìdìbò abẹ́nú gómìnà ẹgbẹ́ APC ní ìpínlẹ̀ Osun lọ́la
- Wo àwọn ewu àti ànfàní márùn ún tó wà nínú igbó mímu
- Ìyá ẹni ọdún 102 kéde ìpinnu rẹ̀ láti díje du ipò Ààrẹ Naijiria lọ́dún 2023
- Òní ní Oloye Christopher Adebayo Alao Akala yóò wọ káà ilẹ̀ lọ ní Ogbomoṣo
- Ẹnikẹ́ni tó bá tún fi ìyà jẹ òṣìṣẹ́ LASTMA l'Eko yóò fojú winá òfin- Ọ̀gá LASTMA
- Yàtọ̀ sí Bimbo Success àti Kemi Korede, wo àwọn míì tí wọ́n ń pariwo Funke Akindele kiri
- Àwọn òṣìṣẹ́ wa kò lọ́wọ́ nínú gbígbé egbògi olóró - NDLEA
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá dárúkọ àwọn ọlọ́pàá mẹ́rin tó ń bá Abba Kyari ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń gbé oògùn olóró
- Títí di àsìkò yìí, a kò tíì mọ̀ eèyàn ti òkú náà jẹ́ ṣùgbọ́n a ti bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ ìwádìí tó yẹ Ogá Ọlọ́pàá Ogun
Ọgbẹni Umar sọ pe bi ago marun un ìdajì ni iṣẹlẹ ọhun ṣẹlẹ.
O ni o nira lati sọ ni pato iye awọn eeyan to fara kaasa ninu ijamba ọkọ naa.
Umar ṣalaye pe ere asaju lo jẹ kí ọkọ akero ọhun kọlu tanka agbepo eleyii to jẹ ọkọ mejeeji gbana.
Ọga ajọ FRSC ni oun ko le sọ pato ọkọ to jẹbi ninu awọn mejeeji.
Umar ni ọna Ibadan ni ọkọ akero naa mori le nigba ti tanka agbepo n bọ wa sí ilu Eko.
Nọmba ọkọ akero Mazda naa ni ZT 28 KLD nigba ti ko si nọmba lara tanka.
Ọgbẹni Umar sọ pe obinrin kan, ọkunrin kan ati ọmọde nikan ni eeyan le damọ ninu awọn to ku nibi iṣẹlẹ naa.
Ọga ajọ FRSC nipinlẹ Ogun ni ijamba ọhún ko ba ti ṣẹlẹ ti awọn awakọ mejeeji ba tẹle ilana ọkọ wiwa loju popo ni.
Umar kẹdun pẹlu awọn ẹbi awọn eeyan to doloogbe ninu ijamba ọkọ naa.
- Ìyá ẹni ọdún 102 kéde ìpinnu rẹ̀ láti díje du ipò Ààrẹ Naijiria lọ́dún 2023
- Ǹjẹ́ ó mọ̀ nípa Álífábẹ́ẹ̀tì Oduduwa àti bí o ṣe lè lòó fi gbé èdè Yorùbá ga?
- Wo ohun tí ìjọba ṣe fún akẹ́kọ̀ọ́ kílààsì SS 2 tó gbá Olùkọ́ létí ní Ibadan
- Gómìnà Zulum ṣe ìkìlọ̀ lórí ìdúnkookò ikọ̀ agbéṣumọ̀mí ISWAP sí Nàìjíríà
- Wọ́n ti fi orúkọ Sadio MAne sọ pápá ìṣeré kan ní Senegal















