Yàtọ̀ sí Bimbo Success àti Kemi Korede, wo àwọn míì tí wọ́n ń pariwo Funke Akindele kiri

Oríṣun àwòrán, Others
Báyìí ni Funke Akindele ṣe sanwó ìwòsàn ọmọ mi - Bimbo Success
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní kò ní burú títí kó má ku ẹnìkan mọ́ni ẹni tí yóòkù la ò mọ̀.
Gbajúgbajà òṣèré tíátà, Bimbo Success tí kọrin ìyìn kí akẹgbẹ́ rẹ̀ Funke Akindele fún ìrànlọ́wọ́ tó ṣe fún un lórí àwọn ìbejì rẹ̀.
Ní ọjọ́ Ìṣẹ́gun, ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù kejì ní Bimbo Success kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwúrí nípa Funke Akindele sórí ẹ̀rọ ayélujára Instagram rẹ̀ láti fi gbóríyìn fún Funke nípa bó ṣe san mílíọ̀nù kan náírà fún ìwòsàn ọmọ rẹ̀.
- Ẹ̀kún omi gbé èèyàn méjìdínlógójì lọ nílùú Petrópolis ní orílẹ́èdè Brazil
- Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀
- Ẹ̀yin ará ìlú ẹ má bìnú, kìí ṣe pé a mọ̀ọ́mọ̀ kó epo tí kò dáa wọ Naijiria
- Gómìnà Zulum ṣe ìkìlọ̀ lórí ìdúnkookò ikọ̀ agbéṣumọ̀mí ISWAP sí Nàìjíríà
- Ìwádìí tó kúná ni a fẹ́ láti mọ̀ àwọn Onígbọ̀wọ́ olóògùn owó ní Oja Odan- Oba Oladiipo Oyebamiji
- Algeria yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní san N41,000 fáwọn ọ̀dọ́ tí kò rí iṣẹ́ ṣe lóṣù tó ń bọ̀
- Amotekun Ondo gbẹ́sẹ̀lé ọkọ̀ àjàgbé tó ń kó àwọn ọ̀dọ́ 63 láti Gombe lọ sí Eko
Kí ló ṣe Bimbo Success?
Bimbo ní òun ń bá Funke sọ̀rọ̀ lórí fóònù ló gbọ́ tí ọ̀kan nínú àwọn ìbejì òun ń wúkọ́ lemọ́lemọ́ tó sì ní, Bimbo ikọ́ yìí ti pọ̀jù.
Ó ní òun fèsì pé òun ti gbé ọmọ náà lọ sí ilé ìwòsàn ṣùgbọ́n Funke ní dandan à fi kí ń máa gbe bọ̀ ní ilé ìwòsàn kan tó wà ní Lekki.
Bimbo ni pe: "Ní ọjọ́ kejì ni mo lọ nítorí ilẹ̀ ti ṣú lálẹ́ ọjọ́ náà, nǹkan bí ago méjìlá ààbọ̀ ni àmọ́ títí ilẹ̀ fi mọ́ Funke pè mí tó ìgbà mẹ́fà kódà èmi ni mó ń sọ fún un pé kó lọ sùn.
"Nígbà tí mo dé ilé ìwòsàn, wọ́n ní wọ́n máa dá wa dúró ni, nítorí náà kí n san owó àsansílẹ̀, owó náà sì pọ̀, Funke ní kí n gbé fóònù fún dókítà tó sì sọ fún wọn pé kí wọ́n fún wa ní ìtọ́jú tó péye.
Bakan naa ni Bimbo ni: "Nígbà tí mò ń lọ sí ilé ìwòsàn, mi ò mú aṣọ mìíràn tí mo le wọ̀ dání ṣùgbọ́n lẹ́sẹ̀ kan ni Funke ti ní kí wọ́n lọ ra aṣọ fún èmi, àwọn ọmọ mi, naní àti àbúrò mi tó wà pẹ̀lú mi."
"Lẹ́yìn ọjọ́ karùn-ún ni wọ́n dá wa sílẹ̀, mílíọ̀nù kan náírà ní owó tí wọ́n ní a máa san àmọ́ dókítà ní Funke ti san. Ó yàmí lẹ́nu gan."
Bawo ni Bimbo ṣe rọ̀jò àdúrà fún Funke Akindele
Lẹ́yìn tí Bimbo ṣàlàyé bí iṣú ṣe kú àti bí ọ̀bẹ ṣe bẹ́ ló bẹ̀rẹ̀ síní rọ̀jò àdúrà fún Funke Akindele.
Ó ní "Lafunky, o ò ní sunkún lórí àwọn ọmọ rẹ̀, aṣọ tó bo ìhòhò rẹ kò ní fàya, òpó tí Olufunke fẹ̀yìntì kò ní wó lágbára Ọlọ́run."
Ní agbára Ọlọ́run, tí Olufunke bá gbẹ́lẹ̀ yóò kan omi, Olufunke yóò gbìn, yóò kó èrè tó pọ̀, Ọlọ́run yóò ṣí ilẹ̀kùn àánú fún ìwọ àti ìdílé rẹ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 1
Àwọn tí Funke Akindele ti ṣore fún sẹ́yìn:
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan ti fi onírúurú ìròyìn tí kò dára síta nípa Funke Akindele sẹ́yìn, lára rẹ̀ ni nígbà tí ọ̀kan nínú àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí nínú oṣù kẹfà, ọdún 2021 sọ pé Funke Akindele ṣòro bá ṣiṣẹ́.
Jú gbogbo rẹ̀ lọ, àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ ń kọrin yin Funke Akindele lẹ́ nu ọjọ́ mẹ́ta yìí.
Yàtọ̀ sí Bimbo Success, Kemi Korede àti adẹ́rìnínpòṣónú Princess náà kọ àwọn ọ̀rọ̀ ìwúrí àti idúpẹ́ sí Funke Akindele lórí Instagram.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Kemi Korede kò sọ oore tí Funke Akindele ṣe fún un, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀ fún ipa tó kó nínú ayé rẹ̀ lásìkò tó ní ìpèníjà.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 2
Bákan náà, adẹ́rìnínpòṣónú Princess níbi ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan sọ ipa tí Funke Akindele kó fún òun nígbà tí òun àti ọkọ rẹ̀ ń kọ ara wọn.
Ta ni Bimbo Success?
Gbajúgbajà òṣèré tíátà ni Bimbo Success.
Ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù kọkànlá ni wọ́n bi i.
Bàbá rẹ̀, Adebayo Success ló dá ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ onímọ́tò NURTW sílẹ̀.
Lọ́dún 2016 ló ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú Saheed Bolaji Oscar tí òun náà jẹ́ adarí eré tíátà Yorùbá .
Nínú oṣù kọkànlá, ọdún 2021 ni Ọlọ́run fi ìbejì, ọkùnrin méjì ta wọ́n lọ́rẹ.






















