Oduduwa alphabets: Ǹjẹ́ ó mọ̀ nípa Álífábẹ́ẹ̀tì Oduduwa àti bí o ṣe lè lòó fi gbé èdè Yorùbá ga?

Njẹ o mọ pe alifabẹẹti Oduduwa wa yatọ si alifabẹẹti ede Yoruba ati Oyinbo?
Ọpọ ọmọ Yoruba ni ko mọ pe alifabẹẹti tiwa n tiwa ti wa tipẹ lati aye Odududuwa to jẹ baba gbogbo ẹya Yoruba.
Koda o ni ilana iwe kikọ to jẹ ti Yoruba gan an tawọn Yoruba ti n lo ṣaaju alifabẹẹti tawọn Oyinbo gbe wa ninu ede Yoruba ati ede Gẹẹsi.
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjà ti bẹ́ sílẹ̀ láàrín Pasuma àti 'Manager' rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ owó?
- Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kogi buwọ́lu ₦30,000 owó oṣù òṣìṣẹ́ tó kéré jùlọ
- Amotekun Ondo gbẹ́sẹ̀lé ọkọ̀ àjàgbé tó ń kó àwọn ọ̀dọ́ 63 láti Gombe lọ sí Eko
- Ẹ̀yin ará ìlú ẹ má bìnú, kìí ṣe pé a mọ̀ọ́mọ̀ kó epo tí kò dáa wọ Naijiria
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá dárúkọ àwọn ọlọ́pàá mẹ́rin tó ń bá Abba Kyari ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń gbé oògùn olóró
- Olùkọ́ lu akẹ́kọ̀ọ́ rẹ ọmọ ọdún kan àti oṣù méje pa ní ìpínlẹ̀ Delta, O bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá
- Àgbáríjọpọ̀ èèyàn sẹkúpa ọkùnrin kan lórí ẹ̀sùn pé ó dáná sun Kurani
Ile ẹkọ kan to n ṣe agbatẹru kikọ Alfabẹẹti Oduduwa, Oduduwa Alphabetic Academy School wa ni Ajase ni orilẹ-ede Benin Republic nibi ti wọn ti tan mọ iran Yoruba.

Ni bayii, ile ẹkọ naa n ṣe ayẹyẹ ikẹkọọ gboye alakọkọ iru rẹ ni fasiti OAU ni ILe Ife lọjọ kẹtadinlogun, oṣu keji, ọdun 2022

Bakan naa ni wọn tun ṣe ajọdun ọdun mẹfa ti wọn da ile ẹkọ ọhun silẹ


Wọnyii diẹ lara awọn fọto lat ibi ayẹyẹ ikẹkọọ jade ni ile ẹkọ naa.

Oloye Popo Toluwalase ni o ṣe agbateru ile eko naa ti ọpọ ọmọ Yoruba atata ti kẹkọọ gboye bayii.

Ilé ẹ̀kọ́ Oduduwa Alphabetic Academy ṣe ayẹyẹ ìkẹ́kọ̀ọ́ fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní Benin Republic lati tubọ gbe ogo aṣa ati igbagbọ Yoruba ga kaakiri agbaye.

Okan lara awọn to tun sọrọ itẹsiwaju nibi eto naa ni komiṣọnna aṣa ati irinajo afẹ fun ipinlẹ Osun, Ogbeni Obawale Adebisi.

Komiṣọnna naa to ṣoju gomina Gboyega Oyetola nibẹ sọrọ nipa pataki kikọ awọn ọdọ asiko yii nipa ede Yoruba sii ki iwa ọmọluwabi le pada si awujọ wa.














