Minimum Wage: Ìjọba ìpínlẹ̀ Kogi buwọ́lu ₦30,000 owó oṣù òṣìṣẹ́ tó kéré jùlọ

Oríṣun àwòrán, @OfficialGYBKogi
Gomina ipinlẹ Kogi, Yahaya Bello ti buwọlu ẹgbẹrun lọna ọgbọn naira gẹgẹ bii owo oṣu to kere julọ fun awọn oṣiṣẹ ni ipinlẹ naa.
Akọwe ijọba ipinlẹ ọhun, Folashade Arike Ayoade lo kede igbesẹ yii lẹyin ipade kan pẹlu ẹgbẹ oṣiṣẹ niluu Lokoja.
O ni ajakalẹ arun Covid-19 to mi gbogbo agbaye titi lo ṣokunfa bi awọn ko ṣe tete gbe igbeṣe lori owo oṣu tuntun naa, eyii ti awọn ti bori rẹ bayii.
- Ìjọba Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19
- Nnamdi Kanu yóò tún fojú balé ẹjọ́ lónìí, oun tó lè ṣẹlẹ̀ rèé
- EFCC gbẹ́sẹ̀lé dúkìá ọ̀gá olọgun tí iye rẹ̀ tó ₦10.9b
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
- Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá
- Aregbẹsọla kìí ṣe Olọ́run, iṣẹ́ Oyetola ló máa fọhùn lọ́jọ́ ìdìbò- Ismail Omipidan
- Wo ohun méjé tó yẹ kí o mọ̀ nípa Abba Kyari, ọ̀gá ọlọ́pàá tí wọ́n fẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn kàn
Akọwe ijọba naa tun gboriyin fun ẹgbẹ oṣiṣẹ ipinlẹ ọhun fun ifọwọsowọpọ ati suuru wọn.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, ifọwọsọwọpọ ẹgbẹ naa lo mu ki awọn ṣe aṣeyọri lori igbesẹ tuntun naa.
Nigba to n sọrọ, igbakeji gomina ipinlẹ Kogi, Edward Onoja gboriyi fun awọn oṣiṣẹ ijọba ipinlẹ ọhun fun akitiyan ati ifọwọsọwọpọ wọn pẹlu ijọba lori ọrọ naa.
O ni inu oun dun pe wọn ko jẹ ki ọrọ naa yọri si iyanṣẹlodi ki awọn to yanju rẹ.
Lẹyin naa lo juwe gomina Yahaya Bello gẹgẹ bii adari rere, ati ẹni to ni ifẹ awọn oṣiṣẹ rẹ lọkan.
Ẹwẹ, alaga ẹgbẹ awọn oṣiṣẹ, NLC, ẹka Kogi, Onuh Edoka sọ pe inu oun dun pe awọn oṣiṣẹ ipinlẹ Kogi ti ba awọn ojugba wọn lawọn ipinlẹ mii dọgba bayii nipa owo oṣu naa.















