Democarcy Day: Àwọn ọ̀rọ̀ tí Bola Tinubu fi ránṣẹ́ lórí àyájọ́ ìjọba alágbádá rèé

Oríṣun àwòrán, Tinubu
Asíwájú Bola Ahmed Tinubu, to jẹ́ èèkàn nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC ti ní àwọn tó le sọ àwọn ènìyàn di òtòsì àti àláìmọ̀kan, ni àwọn ń bá figagbága.
Bí orílẹ̀-èdè Naijiria ṣe ń ṣe àyájọ́ ìṣèjọba àwa ara wa ni Asiwaju ń ké pe àwọn ọmọ Nàìjíríà láti dúrò tí ètò ìjọba àwa arawa wámúwámu.
Tinubu pe ipe yìí lọjọ́ Eti pẹ̀lú àfikún pé, ètò ìjọba àwa arawa, pẹ̀lú iṣèjọba rere a ma mú ojúùtú bá ìpèníjà tó le ṣúyọ.
Àwọn ìtàn mánigbàgbé tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- ₦324bn la pín fún 136,000 oníṣòwò ké kè ké lásìkò ìgbélé Covid-19 - Buhari
- Wo ibi tí ìpalẹ̀mọ́ fún ìwọ́de June 12 dé dúró ní Nàíjíríà àti òkè òkun
- Ọ̀rọ̀ díẹ̀ ati ìgbésẹ̀ akin lá máa gbé báyìí lórí ọ̀rọ̀ Nàíjíríà - Obasanjo
- Wo ipa mánigbàgbé táwọn ààrẹ ní sáà ìjọba alágbádá kẹ́rin ṣe
- Wo àwọn ààrẹ alágbádá tó ti jẹ ní Nàìjíríà láti 1960 di àkókò yìí
- MKO Abiola, iṣẹ́ aṣẹ́gità ló fi bẹ̀rẹ̀ okoòwò
Ó ní bí ìdójúkọ ṣe tílẹ̀ pọ̀ tó, tó sì ń kojú olúkúlùkù, síbẹ̀ Nàìjíríà gbọdọ̀ dúró ti ètò ìjọba àwa ara tó múná dóko.
Gómínà ìpínlẹ̀ Eko nígbà kan rí tún rọ Nàìjíríà láti dìde lòdì sí òhunkóhun tó le yí omí àláfíà ètò ìjọba àwa arawa dànù.
Asiwaju rọ wọ́n láti díde lòdì sí ìwà ipá àti jàgídíjàgan àti gbogbo àwọn gbọ́yìsọ̀yí, tí wọ́n ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu wọn dá wàhálà sílẹ̀ láàrín àwùjọ Nàìjíríà.
"Àwọn tí á n bá jà ni àwọn tó n sọ ènìyàn di alámọ̀kàn ati òtòsì. A ń ṣe àyájọ ọjọ́ ìṣèjọba àwa arawa kìí ṣe nítórí pé àti rìn jìnà nínú rẹ̀, bí kò ṣe pé kí a ní ìwúrí láti túbọ̀ tẹ̀síwájú.
Nàìjíria sì ni ọ̀nà tó jìn láti lọ, àt ibi gíga láti dé àti láti jọ jùmọ̀ ṣe òhun rere bí orílẹ̀-èdè àti ẹ̀yà èèyàn kan." gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Tinubu
Asiwaju ẹgbẹ́ òṣèlú APC náà rọ ọmọ Nàìjíríà láti ránti MKO Abiola, tó ìjáwé olúborí ni June 12, 1993 tí wan sì jí àṣeyọrí rẹ̀ mọ lọ́wọ́.
Ó ní "Abiola kò káárẹ̀, sùgbọ́n ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ kí gbogbo ènìyàn báa le jẹ àǹfàní ètò ìjọba àwa-arawa tí wọn gbà lọ́wọ́ rẹ̀."
Tinubu ni láísì ìrúbọ́ tí Abiola ṣe kò ni si àjọtọ̀ June 12 lónìí.
- Ìjà Awolowo, Akintola àti ogun 'Wẹtiẹ', ẹ̀kọ́ wo ló kọ́ wa?
- Wo ìṣẹ̀lẹ̀ márùn-ún tí kò bá pín Nàíjíríà sí yẹ́lẹ-yẹ̀lẹ
- Taiwo Akinkunmi, ọmọ Ibadan tó ya àsìá Naijiria
- Alimotu Pelewura, Ìyálọ́jà akọ́kọ́ l’Eko tó mi amúnisìn àti ìjọba tìtì
- Ìdílé márùn-ún tó gbajúmọ̀ fún òwò ẹrú nílẹ̀ Yorùbá
- Ogun Àgbẹ́kọ̀yà, ìjà òmìnira fáwọn àgbẹ̀ ni àbí ìfẹ̀míṣòfò?
Asiwaju wa rọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà láti ránti àwọn ẹlòmíràn tó ti rúbọ láti mú kí ìjọba àwa-arawa wáyé ni Nàìjíríà.
"Ọnà àtàta láti buyì fún ènìyàn kìí ṣe nípa pípé orukọ wọ́n nìkàn, bí kò ṣe nípa kíké pe ẹ̀mí wọ́n àti ìrétí wọ́n nínú ọ̀rọ̀ àti ìṣe wa.
"Láti dí onígbàgbọ́ nínú ìjọba àwa-arawa, a kọ́kọ́ gbọdọ jẹ́ ọmọ Nàìjíríà.

















