Yoruba Nation Rally: Ṣé lóòtọ́ ni Sunday Igboho darapọ̀ mọ́ ìwódé Yoruba Nation ?

Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni asaaju ajijagbara Yoruba Nation, Oloye Sunday Igboho ti gunlẹ si adugbo Ojota nilu Eko nibi ti iwọde naa ti n waye.
Agbẹnusọ fun Igboho, Olayomi Koiki lo kede bẹ loju opo Facebook rẹ.
Koiki ni awọn alatilẹyin Sunday Igboho ti de sinu Eko lati wa darapọ mọ iwode Yoruba Nation to n lọ lọwọ ni ilu Eko.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ta a ló yìnbọn pa Jumoke, ọmọ ọdún 14 nítòsí ibi ìwọ́de Yoruba Nation ní Ojota?
- Wo ohun tó yẹ ko mọ̀ nípa Saheed Adigun (Adogan) tó kú nílé Sunday Igboho
- Bí Igboho kò bá jáde, àwa yóò jáde fúnra wá, ìyà pọ̀ - Oluwọde Yoruba Nation
- Sunday Igboho ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀kan lára àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tí DSS pa
- "DSS yin ọta ìbọn 48 sí Adogan, kò sì kú, ni wọn bá fi ọmọ odó fọ lórí"
- "DSS tó kọlu ilé Sunday Igboho dàbí pé wọ́n gbé ‘Map’ ilé náà lọ́wọ́ ni"
- Ìlérí ta ni yóò ṣẹ láàrin àwọ̀n olùwọ̀de Yoruba Nation àti ọlọ́pàá?
- Nnamdi Kanu áti IPOB burú ju Boko Haram, agbébọn lọ - Nasir El-Rufai
- DSS kò mú mi lọ́dọ̀ Guru Maharaji, èmi rèé n‘Ibadan, ẹ sinmi àhesọ ọ̀rọ̀ - Sunday Igboho
- Bí ìjọba Buhari bá yege láti pa mí ni, yóò ní ‘Unknown Gunmen’ ló wá pa mí - Sunday Igboho
O ni awọn ko ba ti ija wa, awọn fẹ wa ṣe iwọde ni irọwọrọsẹ ni lati pe fun idasilẹ orilẹede Yoruba.

Iwọde si ti doju ọgbagade nilu Eko bayii nibi ti awọn agbofinro duro wamu wamu lati da awọn oluwọde naa lẹkun.
Bi wọn se n yin afẹfẹ tajutaju si wọn, naa ni wọn n fọn omi gbigbona si wọn lara, ti iro ibọn si tun n dun bakan naa.
Bakan naa ni wọn fi kun wi pe Sunday Igboho kii ṣe ọdaran nitori naa ki awọn eniyan ma a reti wọn ni ilu Eko.
Amọ ṣa, titi di asiko ti akọroyin BBC Yoruba kuro nibi ti iwọde naa ti waye ni ọsan oni, ko ko firi tabi fi oju ri Sunday Igboho.


















