Lagos bulding collapse: Mo gbàdúrà kí Ọlọrun tu gbogbo ẹbí Osibona nínú - Abiodun

Prince Dr. Dapo Abiodun - MFR

Oríṣun àwòrán, Prince Dr. Dapo Abiodun - MFR

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Gomina ipinlẹ Ogun, Dapo Abiodun ti ṣabẹwo si oloye Emmanuel Osibona, to jẹ baba to bi Femi Osibona to kọ ile alaja mọkanlelogun to da wo niluu Eko.

Abiodun lo kede ọrọ naa loju opo Facebook rẹ, to si fi aworan bo ṣe baba agba naa kẹdun iku ọmọ rẹ lede.

O ni "Lalẹ ana ni mo ṣabẹwo si Baba Ijọ Our Saviour's Anglican Church to wa ni Ikene, oloye Emmanuel Osibona, to jẹ baba oloogbe Olufemi Adegoke Osibona."

"Ọgbẹni Osibona ni alaṣẹ ileeṣẹ Fourscore Homes to jade laye lẹyin to ha sabẹ ile alaja mọkanlelogun to da wo naa."

Abiodun tẹsiwaju pe "Mo ba Baba kẹdun lori iṣẹlẹ ibi naa, mo si tun gbadura pe ki Ọlọrun tu oun atawọn mọlẹbi ninu lori iṣẹlẹ laburu naa."

Prince Dr. Dapo Abiodun - MFR

Oríṣun àwòrán, Prince Dr. Dapo Abiodun - MFR

Ti ẹ ko gbagbe, ọjọ kinni, oṣu Kọkanla, ọdun 2021 yii ni ile naa dawo, to si wo pa nnkan bii ogoji eeyan, bo tilẹ jẹ pe wọn ri awọn eeyan gbe jade labẹ ile ọhun laaye.

Àkọlé fídíò, 'Wọ́n gba irun abẹ́ wa, irun abíyá wa, a lọ búra, ilé "Nylon" la tún ń gbé ni Mali fi ṣe iṣẹ́ aṣẹ́wó'

Lara awọn to ba iṣẹlẹ naa lọ ni ọpọ oṣiṣẹ to n ṣiṣẹ ninu ile naa lasiko to da wo, to fi mọ Femi osibona to ni ile naa.

Lẹyin ti ile ọhun dawo, ọpọ eeyan lo sọ pe igb akeji Aarẹ, Yemi Osibanjo lo ni ile ọhun lẹyin to ra ile rẹ lọwọ baba olowo, Micheal Ade Ojo ti ọpọ mọ si Elizade.

Ṣugbọn Osibanjo ati Elizade ti sọ pe awọn ko mọ nnkankan nile naa, ati pe awọn kọ ni wọn ni.

Àkọlé fídíò, Wòólì Alfred kú lọ́dún 1964, ó tún padà wà sí ìlú Agelu f'ọ́jọ́ mẹ́rìnlá!