Prison Break in Nigeria: Ka nípa iye ìgbà tí ikọlu wáyé láwọn ọgbà ẹwọn Nàìjíríà

Ogba ẹwon

Oríṣun àwòrán, @others

Ikọlu sawọn ọgba ẹwọn Naijiria ko jẹ tuntun.

Bi iṣẹlẹ yi ṣe n waye ni lemọlemọ jẹ ohun to n kọ awọn ọpọ lominu.

Lootọ ijọba a maa sọ pe awọn ko ni foju ẹlẹ wo awọn to ba ṣe ikọlu si ọgba ẹwọn sugbọn ko jọ pe awọn araabi ka ihalẹ yi kun.

Ikọlu kan waye laipẹ yi ni ọgba ẹwọn to wa ni Kabba nipinlẹ Kogi nibi ti awọn okere tan ẹlẹwọn ojilerugba sa mọ awọn alaṣẹ lọwọ.

Ikọlu yi la gbọ pe awọn agbebọn ṣe si ọgba ẹwọn naa.

Yatọ si ikọlu yi, ẹ jẹ ka wo awọn miran to ti waye ṣaaju ni Naijiria.

Àkọlé fídíò, Jẹ́ ká lọ sílu mi: Kò sí ìtàn Ibadan láìsí Efunsetan, Òkè méje, Bower's Tower àtàwọn ǹkan

Ikọlu si ọgba ẹwọn Bauchi

Ikọlu yi waye lọjọ Keje oṣu Kẹsan ọdun 2010 nigba tawọn agbebọn aadọta kọlu ọgba ẹwọn to wa ni Bauchi.

Wọn fura si pe awọn ọmọ ikọ agbesunmọmi Boko Haram lo ṣe ikọlu yi.

Awọn ẹlẹwọn 721 lo ribi salọ, wọn pa marun un ninu wọn ti mẹfa si farapa.

Àkọlé fídíò, Femi Falana: Mẹ̀kúnnù gbọ́dọ̀ ṣetán láti gba ẹ̀tọ́ wọn, ìjọba ti kùnà lórí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn

Ikọlu ọgba ẹwọn Ogun

Ni ọjọ Kẹrin oṣu kini ọdun 2013 iroyin gbode pe awọn kan ṣe ikọlu si ọgba ẹwọn Sagamu Minimun Prisons.

A ko ri aridaju awọn to wa nidi isẹlẹ yi amọ awọn ẹlẹwọn ogun ribi salọ ti ọpọ oṣiṣẹ ẹlẹwọn si farapa.

Àkọlé fídíò, Suicide Prevention: ìwọ́de yìí wáyé láti gbógun ti pípa ara ẹni

Ikọlu si ọgba ẹwọn Ondo.

Awọn afurasi adigunjale ni wọn fura si pe o wa nidi ikọlu yi.

Lọgbọnjọ, oṣu Kẹfa, ọdun 2013 si lo waye.

Ninu ikọlu ọgba ẹwọn Olokuta Medium Security Prison to wa ni Akure, awọn aadọta agbebọn lo ṣe iṣe aburu yi.

Àkọlé fídíò, Oloye Peter Fatomilola: Ọjọ̀gbọ́n olùkọ́ni ni Jesu àti Orunmila jẹ́, àwòkọ́ṣe sí rere si n

O kere tan awọn ẹlẹwọn 175 lo ribi salọ.Eeyan meji ku ti ẹnikan si fara pa.

Ọgba ẹwọn Eko naa faragba ikọlu.

Lọjọ Kẹwaa, oṣu kẹwaa, 2014 ni Eko faragba ikọlu si ọgba ẹwọn to wa Kirikiri.

Awọn ẹlẹwọn ogun lo ba ikọlu yi lọ ti awọn farapa si to ọgọrin.

O ṣeni laanu pe awọn mejila ribi salọ ninu wọn.

Àkọlé fídíò, Ijesha tennager police death: O yẹ kí wọ́n máa yẹ ọpọlọ ọlapàá wò kí wọ́n tó gbà wọn síṣẹ

Ikọlu ọgba ẹwọn Kogi

Ninu oṣu kọkanla, ni ikọlu waye si ọgba ẹwọn ijọba apapọ to wa ni Kotonkarfe ni ipinlẹ Kogi.

Afurasi ọmọ ikọ Boko Haram ni wọn lo ṣe iṣẹ yi.

Awọn ẹlẹwọn mẹrinlelogoje lo sa mọ awọn agbofinro lọwọ nigba ti wọn si ri ọkan pa ninu wọn.

Ikọlu ọgba ẹwọn Ekiti

Ni ọgbọn ọjọ, oṣu Kọkanla ni ikọlu waye ni ọgba ẹwọn ijọba apapọ to wa ni Ado Ekiti.

Oṣiṣẹ ọgba ẹwọn kan ba iṣẹlẹ yi lọ.

Ni meni meji wọn ka ẹlẹwọn ọọdunrun le mọkanlelogoji to sa lọ.

Àkọlé fídíò, Abiodun Duro Ladiipo, Moremi: Ǹ kò pé '40' ti Bàbá fi papòdà ṣùgbọ́n mo kọ̀ láti 'remarry'

Ikọlu ọgba ẹwọn Minna

Ọjọ Kẹfa, oṣu Kejila ni awọn adigunjale kọlu ọgba ẹwọn yi to wa ni Minna olu ilu ipinlẹ Niger.

Wọn pa agbofinro kan,awọn ẹlẹwọn ọtalenigba le mẹwaa si ribi sa lọ

Ikọlu ọgba ẹwọn Kuje

Ni olu ilu Naijiria Abuja ni ikọlu yi ti waye ni ọgba ẹwọn to wa ni Kuje lọjọ Kẹrinlelogun, oṣu Kẹjọ, 2016.

Awọn ogbologbo ẹlẹwọn meji Solomon Amodu ati Maxwell Ajukwu ribi fo igana salọ.

Saaju ni ọjọ kọkandinlọgbọn, osu Kẹjọ, ọdun 2016 yi kanna ni awọn kan gbiyanju lati kọlu ọgba ẹwọn Kuje.

Àkọlé fídíò, Lóòtọ́ orin mi àti Lagbaja jọra ṣùgbọ́n ìyàtọ̀ díẹ̀ wà níbẹ - Labule

Edo

Lọjọ Kọkandilogun, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020 awọn kan to sa sabẹ pe awọn n se iwọde ENDSARS

Kogun ja ọgba ẹwọn to wa ni Benin.

Bẹẹ naa ni wọn yabo ọgba ẹwọn to wa ni Oko.

Lapapọ, ẹlẹwọn ẹgbẹrun meji din mẹsan lo salọ lawọn ọgba ẹwọn wọn yi

Àkọlé fídíò, N kò lè ṣe gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin, ṣùgbọ́n n kò mọ̀ títí tí mo fi ṣe ìgbéyàwó

Ikọlu ọgba ẹwọn Owerri

Lọjọ karun un, osu Kẹrin, ọdun 2021, awọn kan ti wọn fura si pe wọn jẹ ọmọ ikọ alaabo ilẹ Igbo, Eastern Security Network(ESN) se ikọlu si ọgba ẹwọn to wa ni Owerri.

Ado oloro ni wọn lo lasiko ikọlu yi.

O le ẹgbẹrun kan aabọ ẹlẹwọn to ribi sa ninu ikọlu yi.

Àkọlé fídíò, Kola Tubosun: Ọ̀pọ̀ ọmọ òyìnbó ló ń kọ́ èdè Yorùbá, ẹ̀yin ọ̀dọ́ ẹ gbé èdè abínibí lárugẹ