Ban on Open Grazing deadline: Miyetti Allah ní eré lásán làwọn gómìnà gúúsù ń ṣe lórí òfin máse da ẹran nígboro

Awọn maluu nibi ijẹko kan

Oríṣun àwòrán, other

Ọjọ kini oṣu kẹsan ọdun 2021 ni gbendeke ti awọn gomina guusu Naijiria gbe kalẹ lati fopin si dida ẹran jẹ ni gbangba, ti n ṣe kẹrẹkẹrẹ sunmọ etile bayii.

Amọṣa, awọn fulani darandaran lorilẹede Naijiria ti ṣalaye pe ala ti ko lee ṣẹ ni ọrọ naa, awọn gomina naa kan n pa ila sẹnu ni.

Awọn darandaran Fulani labẹ aṣia ẹgbẹ Miyetti Allah ni awọn ko ni lee tẹle ofin naa nitori ọrọ ti kọja lori rẹ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ninu ifọrọwerọ kan pẹlu iwe iroyin Leadership, akọwe apapọ ẹgbẹ Miyetti Allah Kauta Kore, Saleh Hassan ni awọn darandaran Fulani ko ni tẹle ofin naa.

O fi kun un pe igbesẹ titọpasẹ awọn ojuna idaran jẹko ti ijọba apapọ ṣẹṣẹ gbe kalẹ, ni awọn fara mọ.

Àkọlé fídíò, Grace Oyin Adejobi: Bí mo bá tún ayé wá, ọkọ mi ni màá padà fẹ́

Alhassan ni pẹlu aṣẹ irina bo se wu ni ti iwe ofin Naijiria gbe kalẹ, ko si ẹnikẹni to le le awọn lati mase daran jẹ nigboro, awọn ko lee tẹle aṣẹ awọn gomina naa.

Bakan naa lo fi kun un pe, ọgbọn ati da ipo aarẹ pada si ẹkun guusu Naijiria lawọn gomina naa n da ati pe ko lee bọ si.

"Agbara ti wọn n wa ko ni tẹ wọn lọwọ. A ti fi ẹjọ wọn sun Allah lati da ede aiyede silẹ laarin wọn. Nibo ni Sunday Igboho wa bayii? Nibo ni Nnamdi Kanu wa? Gbogbo wọn ti wa ni ẹwọn.

O ni gbogbo awọn to n foro ẹmi awọn darandaran bii Sunday Igboho, Nnamdi Kanu lo ti dero ẹwọn nitori Ọlọrun awọn ko sun.

Bakan naa lo fi kun un pe, gomina ipinlẹ Benue, Ortom pẹlu yoo foju wina idajọ to ba yẹ lẹyin to ba kuro ni ipo.

Ẹgbẹ Miyetti Allah ni bi ajọ EFCC ko ba gbe Ortom lẹyin to ba fi ipo silẹ, awọn funra awọn lawọn yoo ko ikọ fijilante awọn sita lati lọ mu u, ki wọn si faa le ọlọpaa lọwọ.