White Witches Association: Ẹgbẹ́ àwọn àjẹ́ funfun ní àbò tó mẹ́hẹ lè fọ́ Nàíjíríà sí wẹ́wẹ́, ẹ̀jẹ̀ ti pọ̀jù

Aworan eeyan kan to n fo

Oríṣun àwòrán, others

Ẹgbẹ awọn ajẹ funfun lorilẹede Naijiria, White Witches Association of Nigeria (WWAN) ti ṣekilọ pe o ṣeeṣe ki orilẹede Naijiria pin si mẹrin tabi mẹfa o.

Ẹyin naa mi kanlẹ lori ikede yii abi?

Awọn ajẹ funfun naa ni bi iṣẹlẹ ipaniyan lọtun losi se n waye latọwọ awọn agbesumọmi Boko Haram, atawọn agbebọn to n ṣọṣẹ kaakiri pẹlawọn darandaran Fulani, ko ba tete dopin, ọrọ lee bọ sori fun Naijiria.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Agbẹnusọ fun ẹgbẹ naa nigba kan ri, Dokita Iboi Okhue ṣalaye ninu ipade pẹlu awọn akọroyin lẹyin ipade awọn ajẹ naa to waye nipinlẹ Cross rivers ati Kaduna loṣu keji ati ikẹrin ọdun 2021, lo sisọ loju ọrọ naa.

Àkọlé fídíò, Peter Fatomilola: Robbery burú ju Yahoo lọ, iṣẹ́ ọpọlọ lọmọ Yahoo fi ń gba owó ìran baba

Afojusun ipade naa ni lati wa ojutu si bi itajẹsilẹ ṣe pọ lorilẹede Naijiria, ti wọn si ni awọn ri aridaju rẹ pe, bi awọn alaṣẹ ko ba tete wa nnkan ṣe si eto aabo to mẹhẹ naa, o ṣeeṣe ki Naijiria o pin si wẹwẹ.

O ni ọrọ abo to mẹhẹ lorilẹede Naijiria bayii n kọ awọn ajẹ lominu bẹẹ ni gbogbo awọn majẹobajẹ lorilẹede Naijiria lo gbọdọ fọwọsowọpọ pẹlu Aarẹ Buhari nitori ajeje ọwọ kan ko lee gbe ẹru dori.