Baba Ijesha: Adewale Elesho, ààrẹ ANTP sọ̀rọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ Baba Ijesha lẹ́yìn ò rẹyìn

Aarẹ ẹgbẹ awọn oṣere tiata labẹ aṣia ẹgbẹ Association of Nigerian Theater Arts Practictioners, ANTP, Alagba Adewale Ẹlẹshọ, ti ọpọ mọ si Elesho ẹnu n ja waya, naa ti da si ọrọ Baba Ijẹṣa bayii.
Ninu fidio kan to fi sori ayelujara, Elesho ni oun ko fẹ sọrọ lori oun to ṣẹlẹ si Baba Ijẹṣa bikoṣe bi awọn eeyan lawujọ to n pe ohun lọtun losi, lati da si ọrọ naa.
Eleso ni awọn yoo kọkọ le kọlọkọlọ lọ naa, ki awọn to fi abọ sori adiyẹ.
- Ẹ̀sùn gbígbìyànjú láti wọ́lé sí ojú ara ọmọdé pẹ̀lú ìpá àtàwọn ẹ̀sùn mìí tí Baba Ijesha yóò jẹ́ rèé
- Baba Ijesha gba béélì níléẹjọ́ Májísírétì, àmọ́ ọ̀rọ̀ kù kó tó jáde l’àhámọ́
- Iyabo Ojo gbé fídíò jáde nípa bí ọwọ́ ṣe tẹ Baba Ijesha
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Iyabo Ojo fèsì lórí béèlì tí wọ́n fún Baba Ijesha
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Ẹni tó bá ní láàkàyè, a mọ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, àwà ti kọ lẹ́tà, èsì t'Ọ́lọ́pàá sì fún wa rèé - Yomi Fabiyi
- Wo ẹ̀sùn mẹ́rin tí ìjọba fi kan Baba Ijesha àti ìjìyà tí ìkọ̀ọ̀kan ní lábẹ́ òfín
Elesho wa rawọ ẹbẹ si Princess, iya ọmọdebinrin ti wọn fẹsun kan pe Baba Ijesha huwa aṣemaṣe pẹlu rẹ, pe ko jeburẹ lori ọrọ naa, ki o si fi iyedenu nitori pe ọrọ naa ti gbona girigiri ju bi gbogbo awọn eeyan ṣe n sọ lọ.
O ni ki Princess o ro atimaaṣebọ oun ati Baba Ijesha ko fi iyedenu lori ọrọ naa, nitori oju ti ọrẹ mi oju ko timi, onitọun ni ko loju ti niyẹn.

Oríṣun àwòrán, Realyomifabiyi/Instagram
Bakan naa ni gbajumọ oṣere alawada naa tun ke si awọn mọlẹbi ọmọdebinrin naa pe, lootọ ohun to ṣẹlẹ yii ko dun mọ ẹnikẹni ninu ṣugbọn bi a ba ni ka dana sun ejo bo ṣe gun to, afaimọ ka maa da ina sun ile.
"Mo bẹ awọn obi ọmọ ti nnkan ṣẹlẹ si, o jootọ o, ko joo tọ o, wọn ko gbọdọ maa pe eeyan lole, ko tun maa gbe ọmọ ẹran jo.
Ọlọrun nikan lo mọ ohun teeyan ko mọ"
Lẹyin to rọ gomina Babajide Sanwo-Olu lati bawọn foju sunnukun wo ọrọ naa, aarẹ ẹgbẹ oṣere ANTP naa tun ke sawọn ọlọpaa lati wadi ọrọ naa delẹ daadaa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Yomi Fabiyi bá Sanwo-Olu, gómìnà Eko sọ̀rọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Àkúntúnkú, ìgbà mẹ́fà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ rè é tí Shekau kú, tí wọ́n ní kò kú mọ
- Ìrọ́ lẹ pa, ìbò ìjọba ìbílẹ̀ kò ní wáyé l‘Oyo ní Sátidé - APC fárígá
- Èèmọ̀ wọ̀lú! Àwọn jàndùkú jí Adájọ́ gbé lọ nínú kóòtù lọ́sàn án gangan
- Ẹ̀yin tí ẹ sọ pé irọ ni mo ń pa bayii ni yoo ri fún yín
O fi kun un pe, iṣẹlẹ naa fihan pe bi ko ti ṣe rọrun to lati ni orukọ rere, lo ṣe rọrun fun orukọ naa lati bajẹ lẹyin aṣemaṣe kan.



















