Independence Day Nigeria: Lamido Sanusi gbóṣùbà fún ìjọba lórí bó ṣe yọwọ́ ìrànwọ́ epo

Oríṣun àwòrán, @Realshisha
Emir ilu Kano nigba kan ri, Sanusi Lamido ni ọpọ awọn to n kigbe kiri pe awọn n ja fun ẹtọ ẹkun awọn, ifẹ apo wọn nikan ni wọn fẹ.
O ni lẹyin ti wọn ba fi ija ẹlẹmẹya ati ẹsin de ipo ijọba tan, wọn maa bẹrẹ si sin ilu nibamu pẹlu ifẹ ọkan wọn.
Lamido sọrọ yii nibi eto kan ti ijọ Convenant Christian Centre, ti pasitọ Poju Oyemade n dari pe ni ipinlẹ Eko.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Irọ́ ni o! Ìyàwó Ọ̀ọ̀ni Ogunwusi kò bímọ tuntun
- Donald Trump àti ìyàwó rẹ́ ti lùgbàdì àrùn CoronaVirus
- Fídíò rèé lórí bí Sunday Igboho ṣe korò ojú sí ìwà ọ̀dàlẹ̀ nílẹ̀ Yorùbá
- Ìfẹ́ Yorùbá ló mú mi fi ẹ̀mí wéwu láti kojú ajínigbé ní Kishi - Sunday Igboho
- Buhari, ayẹyẹ kí là ń ṣe gan, ṣé ti ìpànìyàn àbí ìjínigbé? - Aráàlú ń bèèrè
- Ẹ fura, làásìgbò le wáyé ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́fà yìí lásìkò ìbò gómìnà Ondo - YIAGA
- Wo ìṣẹ̀lẹ̀ márùn-ún tí kò bá pín Nàíjíríà sí yẹ́lẹ-yẹ̀lẹ
- Bọ́ síta láti ṣe ìwọ́de mọ́ ìjọba Nàìjíríà lónìí, ko rugi oyin - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
- Ẹ̀yin ọlọ́pàá 10,000 tí ọ̀gá ọlọ́pàá gbà ṣíṣẹ́ ní 2019, ẹ padà sílé - Iléẹjọ́ pàṣẹ
Nibi ipade ori ayelujara ọhun, ni wọn ti pe gomina tẹlẹ fun ile ifowopamọ apapọ Naijiria naa, lati wa sọrọ lori ọrọ ija ẹlẹyamẹya ati ẹlẹsin to n fojoojumọ peleke si ni Naijiria.
O ni isoro naa ko fi bẹẹ niṣe "pẹlu awọn eniyan orile-ede yii, bikose awọn ọtọkulu rẹ"
"Mi o lero pe awọn ti wọn ni awọn n ja fun ẹya Hausa, Igbo tabi Yoruba ni ifẹ awọn eniyan naa lọkan.
Ni kete ti wọn ba ti de ijọba tan, imọ ti ara wọn ati ẹbi wọn nikan lo ku.
"Ko si ẹni kankan to n soju Arewa, Guusu tabi Ila oorun, nnkan ti mo nsọ ni pe, wọn ni awọn n soju ibẹ sugbọn irọ ni.
Ninu itan Naijiria, ko ti si ijọba ti ko ni asoju lati gbogbo ẹya Naijiria.

Oríṣun àwòrán, @Realshisha
"Nnkan akọkọ to yẹ ka mojuto ni pe, a gbọdọ gbagbe ero pe nigba ti eniyan ba wa nijọba, lo n jẹ asoju ẹya abi ẹsin rẹ, ko yẹ ki o ri bẹẹ".
Sanusi ni, ọkan lara isoro Naijiria ni ọrọ" Federal Character " lai fi ti ijafafa ati mimọ iṣẹ doju ami ṣe, ko ni itumọ kankan"
Lasiko to n fi iyatọ han laarin iṣẹ aladani ati iṣẹ ijọba, Sanusi sọ pe, o ṣe pataki lati ṣe agbekalẹ ilana ti yoo yọwọ oṣelu kuro patapata ninu iṣẹ ijọba.
O salaye, "O yẹ ki a ni" federal Character, sugbọn ki lo de ti a ni minisita, to mọṣẹ rẹ doju ami, to si n mu esi jade, sugbọn ti a tun ni minisita miran ti ko le gbe nkan tuntun ṣe?
Ki lo de to jẹ pe ẹya ni "Federal Character n gbajumọ, lai fi ti awọn to mọ iṣẹ naa ṣe si.
Sanusi wa dupe lọwọ ijọba lori bi wọn se yọwọ iranwọ kuro lori epo, o ni nkan to tọ lati ṣe ni, nitori pe, o ti pẹ to yẹ ki ijọba ti ṣe tori bi eto ọrọ aje ṣe ri.

Oríṣun àwòrán, @tundefashola
Ninu ọrọ tirẹ minisita fun iṣẹ ode ati ilegbe, ọgbẹni Babatunde Fashola ni ki awọn ọmọ Naijiria kọju si ijọba ipinlẹ ati ibilẹ, fun ọna abayọ si isoro wọn, kaka ti wọn yoo fi maa di gbogbo rẹ le ijọba apapọ lọrun.
Fashola ni kii ṣe ijọba apapọ lo ni ile ẹkọ alakọbẹrẹ tabi ile iwosan alabọde ijọba ibilẹ.
Ni Naijiria, ile ẹkọ girama to jẹ ti ijọba apapọ ko ju ọgọrun kan ati meje lọ.
"Mo fẹ rọ awọn eniyan lati lọ ka, iwe ofin Naijiria.
O ni ida mẹẹdọgbọn ninu ida ọgọrun ni agbara ti ijoba apapọ ni, ile igbimọ asofin ati ẹka idajọ lo ni eyi to pọju lọ.
Bọ́ síta láti ṣe ìwọ́de mọ́ ìjọba Nàìjíríà lónìí, ko rugi oyin - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá

Ileeṣẹ ọlọpa ipinlẹ Eko ti fi ikilọ sita pe, ki ara ilu kankan maa ṣe kopa ninu iwọde loni tii ṣe ayajọ ominira Naijiria.
Ikilọ yii kun ikede ti ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria lapapọ ti fi sita ṣaaju pe, awọn yoo da ọlọpaa sita jakejado Naijiria lati dena iwa kankan ti yoo ṣakoba fun alafiaa ilu.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọjọ́ ìbí bàbá mi ni aàrùn ọkàn ṣekúpa màmá mi lójijì- Davido
- Ìjọba Kwara kéde ọjọ iwọlé àwọn akẹkọọ lẹyìn ìséde Covid 19!
- Ọ̀pọ̀ aráàlú Owo wà nílé ìwòsàn, síbẹ̀ APC àti PDP kò gba ẹ̀bi
- Makinde gba àwọn òṣìṣẹ́ LAUTECH 41 tí ìjọba Ajimobi dá dúró lẹ́nu iṣẹ́ padà
- Obabinrin Elizabeth kejì kí Nàìjíríà kú oríire òmìnira ọgọ́ta ọdún
Lasiko ipade kan pẹlu awọn ọga ọlọpaa ni ipinlẹ Eko, ni Kọmisana ọlọpaa Eko, Hakeem Odumosu fi ikilọ yi sita.
O ni awọn ko ni fi aye gba akojọ kankan tabi iwọde, to fi mọ ifẹhonu han eyi to le mu ipalara ba iṣọkan Naijiria.

Ẹwẹ, ijọba ipinlẹ Eko fun ara rẹ ati ti ipinlẹ Ogun ti ni, ko ni si afẹfẹ yẹyẹ kankan lasiko ajọdun ominira Naijiria.
Ni ti ipinlẹ Ogun, awọn tun sọ pe, ko ni si lilọ bibọ ọlọkada bẹrẹ lati alẹ ọgbọnjọ oṣu Kẹsan titi di owurọ ọjọ keji oṣu Kẹwa.
Bẹẹ ni wọn ni konileogbele yoo wa lalẹ ọjọ meji, iyẹn ọgbọnjọ oṣu Kẹsan ati ọjọ Kini oṣu Kẹwa
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Ninu awọn to n palẹmọ lati ṣe iwọde lọjọ ayajọ ominira Naijiria ni Omoyele Sowore ati awọn ajafẹtọ ominira mii, labẹ akori RevolutionNow.
Bẹẹ naa ni awọn agbarijọpọ ẹgbẹ ọmọ Yoruba mii naa ni awọn fẹ ṣe iwọde lati beere fun Oduduwa Republic.
- €10,000, ara owó tí wọn fi ra Ighalo pòórá, Ilé aṣòfin Osun bẹ̀rẹ̀ ìwádìí
- Ìwádìí BBC rèé lórí ẹ̀sùn gbájuẹ̀ $120,000 tí wọ́n fí kàn igbákejì olórí òṣìṣẹ́ ìjọba l‘Osun
- PDP àti APC fi ìbọn dárà l'Ondo, ọ̀pọ̀ èèyan farapa, àìmọye dúkìá ṣòfò
- "Dípò ìnákúnàá lórí ìgbéyàwó ọmọ mi, mo lò owó fún ìgbéyàwó ọmọ òrukàn mẹ́tàlá"
- Àwàdà kẹríkẹrì nígbà táwọn olùdíje ààrẹ́ Amerika méjì kọjú ìjà síra wọn
- Ìjọba àpàpọ̀, jọ̀ọ́ máṣe yẹ̀ lórí àdéhùn rẹ fẹ́gbẹ́ òṣìṣẹ́ - Ile aṣojú-ṣòfin
- Ọgọ́rin arìnrìnàjò tó padà wá sí Nàìjíríà ló ní Coronavirus - PTF
Awọn ikede wọn yii, yala lati ọdọ ileeṣẹ ọlọpaa ati awọn ijọba ipinlẹ, lawọn eeyan ti n ṣe eemọ si ṣugbọn ti awọn onwoye ni ko ba ofin mu.
Loju opo Twitter awọn eeyan ti n sọ tẹnu wọn nipa aṣẹ tawọn ijọba gbe kalẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 3
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 4














