Ajimobi Vs Seyi Makinde: Amòfin ní tí Ajimobi bá jẹ́ mẹ̀kúnnù, ṣé Makinde yóò gbà kí wọ́n sín sí GRA?

Oríṣun àwòrán, Ajimobi lives on
Ọrọ ti n ba ọrọ bọ, eegun alare lori igbesẹ ti gomina Seyi Makinde gbe, nipa fifun ẹbi Abiola Ajimobi laaye lati sin oku si ilẹ ijsba GRA, ti ofin ko faaye gba.
Awọn ọmọ Naijiria kan lo fi oju laifi wo igbesẹ naa lori ayelujara, ti wọn si ni igbesẹ arufin gbaa ni Makinde gbe, pẹlu bo se fi ontẹ lu isinku Ajimobi sori ilẹ GRA.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣé ó leè jẹ́ ilẹ̀ tí Makinde kò jẹ́ kí Florence Ajimobi gbà ló ń bi nínú?
- Akinyele tún gbàlejò àwọn mùjẹ̀mùjẹ̀, tìyá-tọmọ̀ fara gbọgbẹ́
- Ẹ pèsè ẹlẹ́rìí púpọ̀ bí bẹ́ẹ̀ kọ́, Sotitobire yóò jẹ́rìí fúnrarẹ̀ o! - Ilé ẹjọ́ ìpínlẹ̀ Ondo
- Ilé ìwòsàn kan rèé tó ń fi àtùpà gbẹ̀bí aláboyún
- Àwọn ìjọba ìbílẹ̀ méjìdínlógún yìí kò tíì lè bọ́ lọ́wọ́ ìséde - Ìjọba àpapọ̀
Idi si ree ti BBC Yoruba fi tọ onimọ kan nipa ofin lọ lati beere pe, se gomina Makinde rufin lootọ abi bẹẹ kọ lori gbigba ki wọn sin Ajimobi si GRA.

Lero ti Amofin Ayodeji Olabiwonninu ni ofin Nigeria Land use act 1978 fun gomina ipinlẹ kọọkan lagbara lati sakoso awọn ilẹ ijọba to wa ni agbegbe rẹ.
O fikun pe, pẹlu ohun gbogbo ti a ri ka ninu iroyin ati ofin ilẹ Naijria, ko yẹ ki Gomina Makinde gba ki wọn sin Ajimobi si GRA Oluyole, to wa ni Ibadan.
Amofin naa ni ''O fihan gbangba pe awọn kan ga ju ofin lọ ati wi pe, ofin orilẹede Naijria ko jọba lori gbogbo eniyan.''

''Ni ọpọlọpọ agbegbe ni Naijiria, awọn eniyan giga ati ọlọla n jọba lori ofin, ti ko si si ẹni ti yoo mu wọn si.''
Amofin Olabiwonninu wa n beere pe, "ka ni mẹkunu ni Abiola Ajimobi, n jẹ ijọba le gba ki wọn sin oku rẹ si GRA?
Ijiya wo lo tosi ẹni to ba ru ofin to lodi si sinsin oku si ilẹ ijọba GRA?
Nigba to n mẹnu ba iru ijiya to tọ si ẹni to ba rufin yii, Olabiwonninu sọ wi pe, ijiya to rọ mọ riru ofin to de bi wọn ṣe n lo ilẹ ijọba yatọ ni agbegbe kan si omiran.
Olabiwonninu ni, gbogbo ofin to ba ti tọka si pe iwa yii ko lẹtọ, naa lo ma n sọ iru ijiya to tọ si ẹni to ba rufin naa ni agbegbe ọhun.

Amọ, o ni ohun to ṣe ni laanu ni wi pe, ijọba lo ma n pe eniyan lẹjọ to ba ru ofin to de lilo ilẹ ijọba.
Sugbọn nibayii, "ijọba ipinlẹ Oyo gan an lo rufin, ta ni yoo wa gbe Gomina Seyi Makinde lọ si ile ẹjọ bayii, lẹyin ti wọn fun ẹbi Abiola Ajimobi laaye lati sin oku si GRA, to wa ni ipinlẹ naa?
Ṣé ó leè jẹ́ ilẹ̀ tí Makinde kò jẹ́ kí Florence Ajimobi gbà ló ń bi nínú?
Awọn ẹri dabi ẹni ti n farahan lori idi ti iyawo gomina ipinlẹ Ọyọ nigba kan, Florence Ajimobi, fi tahun si ijọba ipinlẹ Ọyọ lọjọ Aiku lẹyin isinku ọkọ rẹ.
Ọjọ Aiku ni fidio kan gba ori ayelujara, eyi to ṣafihan Florence, nibi to ti n tahun si igbakeji gomina ipinlẹ Ọyọ, Rauf Olaniyan, pe wọn ko ba oun kẹ́dùn iku ọkọ oun.

Oríṣun àwòrán, @AAAjimobi
Olaniyan naa han ninu fidio naa, ti wọn ká silẹ ninu yara igbalejo kan nile Ajimobi lẹyin eto isinku rẹ.
Ninu ikede kan ti Akọwe iroyin fún Gomina Seyi Makinde, fi sita lo ti dabi ẹni pe ijọba gbiyanju lati wẹ ara rẹ mọ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Atẹjade naa sọ pe gbogbo igbiyanju àti igbesẹ oun lati ṣe atilẹyin fun idile Ajimobi, lasiko to fi wa ni i dubulẹ aisan lo jasi pabo. Ati pe iyawo Ajimobi kò tẹle ilana to yẹ lati fi aisan àti ikú ọkọ rẹ to ijọba ipinlẹ Ọyọ l'eti.
Ninu fidio naa, Olaniyan sọ pe gbogbo ipe ti oun pe si ori ẹ̀rọ ibanisọrọ Florence Ajimobi, ni kò gbé.
Iroyin tun sọ pe Makinde pe igbakeji gomina ipinlẹ Eko ni, ki o to o ri nọ́mbà dokita to n tọju rẹ.
"Ọna ile ijọba ni dokita naa wa, lẹyin ti mo ránṣẹ pé e láti ba mi sọrọ l'ori aisan Ajimobi, ki ọkọ rẹ to jẹ ọkan lara awọn to di ipo mu ninu ise jọba Ajimobi, to sọ fún un pe ko pada, ko si yọ́ wọ ilu Eko."
Koda, igba ti gbogbo igbiyanju mi lati ba Florence sọrọ ja si asán, ni mo pé gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-olu, pe mo fa ohun gbogbo le e lọwọ, ati pe ko ba ipinlẹ Ọyọ tọju Ajimobi daada, ko si jẹ ki n mọ ti wọn ba nilo iranlọwọ mi.
"Iroyin tun sọ pe Makinde pe Arabinrin Florence Ajimobi, nigba to gbọ pe ọkọ rẹ kú, sugbọn ko tun gbe ìpè."Ipinlẹ Edo ni gomina wa nigba to gbọ pe Abiola Ajimobi kú.
Ó pe iyawo rẹ, sugbọn ko gbe ipe. Eyi ko si tun di lọwọ lati ṣe nkan to yẹ.
Loju ẹsẹ lo pàṣẹ pe ki wọn o sọ asia orilẹ-ede Naijiria kalẹ, lati bu ọlá fun." Iroyin sọ pe, afi bi Gomina Makinde ṣe gba ipe lati ọdọ agba oloṣelu kan, pe ko yọnda ilẹ bi plot mejidinlaadọta fun idile Ajimobi.
Adugbo ti ijọba ya sọtọ, ni Agodi GRA, ni ilẹ to to pulọọ́ti mejidinlaadọta naa wa.
- Ìgbà mẹ́jọ tí awuyewuye wáyé lórí ìṣèjọba Ajimobi!
- Ìbẹ̀rùbojo gba ọkàn àwọn olùgbé Eko àti Ogun nítorí adágún omi Ọ̀yan tí yóò di ṣíṣí láìpẹ́
- Bàbá ẹni ọdún 61 bá ọmọ rẹ̀ lopọ̀, ó fún un lóyún l'EkoOṣu Keji, ọdun 2020, ni ijọba Makinde, gbẹsẹ le ilẹ naa, ti wọn sọ pe ọna ti ko ba ofin mu ni Ajimobi fi gba a.
Koda, iroyin sọ pe awọn agbaagba ninu ẹgbẹ oṣelu APC ati PDP, to fi mọ aarẹ Naijiria nigba kan, lo pé Makinde pe ko yọnda ilẹ naa fun wọn lati sin oku Ajimobi si.
Taiwo Adisa sọ pe "ọrọ ilẹ naa wa nile ẹjọ, oun ko si le tapa si àṣẹ ile ẹjọ.
Koda, gomina Abiola Ajimobi lo gbé ijọba ipinlẹ Ọyọ lọ sile ẹjọ lori ọrọ ilẹ naa."
"Ati pe lootọ ni ofin kò gba ki wọn sin oku si adugbo ti ijọba ya sọtọ, ìyẹn GRA."
Ile Ajimobi to wa ni GRA lagbegbe Ring-Road, nilu Ibadan, ni wọn padà sin in si.
Eyi to tumọ si pe o ṣe e ṣe ki ijọba fun wọn ni àṣẹ láti ṣe bẹẹ. Eyi lo si mu ki ọpọlọpọ máa sọ lori ayelujara pe o ṣee ṣe ko jẹ nkan to n bi iyawo Ajimobi ninu gan-an ni pe Gomina Makinde ko jẹ ko gba ilẹ naa to wa ni Agodi GRA ko di tara rẹ.












