Kazeem Alli: Àwọn tọ jí alága NURTW Osun gbé ti bèèrè 15 mílíọ̀nù owó ìtúsílẹ̀

Oríṣun àwòrán, @Alli Kazeem
Awon ajinigbe ti kan si idile oga NURTW nipinle Osun, won beere owo itusile milionu meedogun naira.
Eniyan kan to sunmo molebi olori egbe National Union of Road Transport Workers nijoba ibile Isokan ni ipinle Osun, Kazeem Alli, ni ojo Aje ba BBC sọrọ lori iṣẹlẹ naa.
O sọ pe awon ajinigbe ti beere owo to jẹ milionu meedogun naira (N15m) fun itusile re.
- Wo àwọn olóṣèlú tí àwọn ọmọ Naijiria ti fi aṣọ wọn ṣe yẹ̀yẹ́..-
- Pẹ̀lú ìbẹ̀rùbojo ní orílẹ̀-èdè Ukraine fí ń ṣé ayẹyẹ àyájọ̀ òmìnira
- Àwọn ‘Rev. Sister’ mẹ́rin tí wọ́n jígbé tí gba ìtúsílẹ̀ láìsan owó ìtúsílẹ̀
- Nítorí gbọnmọ-gbọnmọ ìkọlù rògbòdìyàn tó ń wáyé l'Osun, ìjọba ránṣẹ́ ìkìlọ̀ sí àwọn olóṣèlú, ọlọ́kọ̀ èrò
- Awakọ̀ bàálú Ethiopia Airlines sáré kọjá 'Bus-Stop' nítorí pé wọ̀n tí sún lọ
- Ọlọ́pàá tó bá gbá fóònù yin yẹ̀wò, ọdaràn ni – Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá -
Kini ọlọpaa sọ nipa iṣẹlẹ naa?
Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Ọsun ti sọ pe awọn agbebọn kan ni agbegbe Oke Alfa, Apomu ni wọn se ikọlu sí Kazeem Alli pẹlu awọn nkan ìjà olóró bi adà, ti awọn si mu u lọ.
Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa, Yemisi Opalola ninu atẹjade kan tun sọ pe eeyan mẹjọ ni olopaa ti fi panpe òfin mu lori isẹlẹ naa.
Eniyan kan ti ko fe ki iko iroyin BBC News dá orúkọ re so pe awon ajinigbe Alli ti kan si okan lara awon iyawo re, ti won n pe Jemila, ti won si beere owo naa.
Bawo ni wọn ṣe ji Alhaji Kazeem Alli gbe?
Eni to ba BBC sọrọ nipa iṣẹlẹ yi sọ pe, Awọn ajinigbe naa ti kan si awọn ẹbi Alli nipasẹ iyawo re Jemila Alli ti Wọn si ti se ikilo fun won lati ma jẹ ki ẹnikẹni mọ nipa idunadura naa.
O tẹsiwaju pe Wọn ti beere fun miliọnu mẹẹẹdogun naira gẹgẹ bi owo itusile ṣugbọn wọn ko jẹ ki won ba Kazeem sọrọ, latigba ti wọn ti ji i gbe.
Ti won si n gbadura fun ipadabọ rẹ l'ayọ ati alaafia.
Gbogbo igbiyanju wa lati ba Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa, Yemisi Opalola soro lori bóyá wọn ti mo sí idunadura to n lọ lọwọ pẹlu awọn mọlebi Alli ni o já sí pabo ni gba ti a n ko iroyin jo.
Kini ẹgbẹ PDP àti APC n sọ lori iṣẹlẹ yii?
Ẹ̀wẹ̀, ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party ní ìpínlẹ̀ Ọṣun, ti bu ẹnu àtẹ́ lu ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress ní ìpínlẹ̀ Ọṣun, wọn sí so pe ikọlu Kazeem Alli ni ọwọ ẹgbẹ oṣelu won ninu.
Kola Olabisi to je oludamoran fun eto iroyin fun alaga egbe oselu APC l'Osun, Gboyega Famoodun, ti so saaju pe awon afurasi ti o je janduku ẹgbẹ oṣelu PDP ti pa Alli ti o je okan lara awon oloye egbe naa nijoba ibile Isokan.
Sugbon nigba to n fesi si oro naa, agbenuso fun egbe oselu PDP nipinle Osun, Oladele Oluwabamiji, ninu atẹjade kan to fi sita nilu Osogbo, ti sọ pé egbe re ko lowo ninu isele ikọlu naa, o si da APC ati Alága ẹgbẹ́ náà Famoodun lebi fun ipenija eto aabo to n koju ipinle Osun.
Ninu atẹjade náà la tun ri ka pe, Ẹgbẹ Oṣelu PDP so fún ẹgbẹ oṣelu APC pe o jẹ itẹwọgba ikuna nla fun ẹgbẹ wọn ti ohun se ijọba lọwọlọwọ lati ma sọkun bi ọmọ alainibaba lori ọrọ aabo eyiti o jẹ ojuṣe akọkọ fun ijọba ti o ba ni ètò to dara nibikibi ni agbaye.
- Ẹ ṣọ́ra fáwọn ajínigbé tí wọ́n n díbọ́n bíi ọlọ́kadà àti awakọ̀ Kórópé nipìnlẹ̀ Osun
- Pẹ̀lú gbogbo rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ ní Nàìjíríà, APC kójú òṣùwọ̀n láti borí ìdìbò 2023- Adamu
- Ó yẹ kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ gbé àjọ̀ ASUU lọ sílé ẹjọ́ fún ìfàkókò ẹni ṣòfò- Mínístà Adamu
- Ìdí tí a fi lè fi owó kún owó oṣù òṣìṣẹ́ rèé - Ààrẹ Buhari
- Kíni ẹ̀yin rò bí iléesẹ́ Ọlọ́pàá ṣe ń gbẹ̀wù lọ́rùn àwọn Ọlọ́pàá tó bá hù ìwà ìbàjé-
- Àwọn tó sọ pé kò sí owó ní Nàìjíríà àfi ká yáwó ń pa irọ́ fáráàlú ni – Kwankwaso
















