Yollywood: Baba Wande, Kareem Adepoju, Jide Kosoko, Taiwo Hassan, Yinka Quadri àti Alapinni jẹ́ díẹ̀ nínú àwọn àgbà òṣèré májẹ́kòbájẹ̀ àsìkò yìí

Oríṣun àwòrán, Others
Iriri kọja ẹgbẹ abẹwu ni ọrọ awọn agba osere kọọkan jẹ.
Ohunkohun ti eeyan ba yan láayo, o dara lati fi gbogbo ara ṣe e ki o le moke nibẹ.
Opọ agba osere lo ti fi ara ṣiṣẹ ki iṣẹ tiata to de ibi to de duro yii, awọn miran ri re ibi agba n re nigba ti awon mii si wa lori oke eepe.
Diẹ ninu awọn ọpọ osere titata to si wa laye di isinyii ni a ti ri awon ti ọpọ n pe lorukọ ere ori itage bii: Jide Kosoko, Baba Wande, Ogogo, Kura, Oga Bello ati Alapinni Oosa yatọ si awọn mii ti won tun n sise karakara.
- Olólùfẹ́ mi ṣèèsì fi ọkọ́ gbá mi sí gọ́tà, mo rò pé ọlọ́jọ́ dé ni - Iya Osogbo
- Bí mó bá fojú kan Baba Wande lórí ìtàgé, ṣe ní ẹ̀rù máa ń bà mí - Tafa Oloyede
- Ìtàn ìgbé ayé Isola Ogunsola, akọni mánigbàgbé òṣèré tíátà, olórin àti onílù
- Gbajúmọ̀ agbábọ́ọ̀lù ni ǹ bá jẹ́, ká ní ń ko ṣeré tíátà - Bàbá Wande
- Ǹjẹ́ o mọ̀ pé Baba Sala ló kọ́ Sunny Ade nísẹ́?
- Fídíò mánigbàgbé nípa ìgbà ayé Bàbá Sala
- Ǹjẹ́ o mọ àwọn òṣèré bí Oyin Adejọbi, Funmi Martins àtàwọn míì tó ti dágbére fáyé?
1. Kareem Adepoju ti ọpọ mo si Baba Wande:
Baba Wande bẹrẹ si ni di gbajumo leyin to se ere Ti Oluwa ni ilẹ ni ọdun 1993 nigba to kopa gege bii Oloye Otun.
Lara awon ere to ti se ni Ayo ni Mo fe, Abeni, Arugba, Igbekun, Obuko Dudu, Ika Lomo Ejo, Enu Eye, Oba bi Olorun ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Oloye Karem Adepoju ti se ọpọlọpọ ere ori itage, ere sinima ati ere agbelewo.
Iriri to pọ ni Oloye yii ni to si fi n kọ awon ọdọ osere isinyi.

Oríṣun àwòrán, @Kareem Adepoju
2: Jide Kosoko:
Jide Kosoko jẹ ọkan lara agba oṣere ti wọn bi ere ṣiṣe mọ lati ibẹrẹ.
Ojọ kejila, osu kinni ọdun 1954 ni a bii sile ọla nibi to ti kawe to si bẹrẹ ere itage sise lati ọmọ kekere ni Ebutte Metta ni agbegbe to dagba si ni ilu Eko.
O kawe gboye ninu ẹkọ 'Business Administration' lati ile ẹkọ Yaba College of Education ni ipinlẹ Eko.
Leyin naa lo lọ kọsẹ ere itage sii ni Fasiti Olabisi Onabanjo ni Ago Iwoye.

Oríṣun àwòrán, @Jide Kosoko
Jide Kosoko naa bẹrẹ ere tiata pẹlu awọn alarinjo Ifelodun Traveling Theatre Group.
Diẹ lara ere ti Jide Kosoko ti kopa ni ede Yoruba ni: 'Eje Adegbenro', 'Durodola', 'Koseegbe', 'Oro Nla' nigba ti awọn mii lede oyinbo ni 'King of Boys', 'The Bling Lagosian', 'Reunion', ati awon mii.
Awọn ọmọ bibi rẹ obinrin meji naa ni wọn ti darapọ mọ baba wọn lẹnu iṣẹ ere itage. Awon naa ni Sola ati Bidemi Kosoko.
3: Taiwo Hassan- Ogogo Kulodo

Oríṣun àwòrán, @Ogogo
Agba Osere yii jẹ ọkan lara awọn agba oṣere ti aye n fẹ lasiko yii.
Opọ maa n yin fun ọgbọn atinuda to fi maa n gbe ero rẹ kalẹ ninu ipa ti wọn ba fun Ogogo ṣe.
Wọn maa n sọ pe kii fẹ ko ipa ti yoo ti maa tẹnubọ osere binrin mii lẹnu rara.
Ojọ kọkanlelọgbọn, osu kẹwaa, ọdun 1959 ni wọn bi Ogogo ni ilu Ilaro.
O lọ sile ẹkọ Christ Church School ati Yaba Technical College ninu iṣẹ atun ọkọ ṣe ti won pe ni 'automobile mechanic'.
Ogogo ba ileeṣẹ Water Corporation sise fun ọdun mẹtala lati 1981 si 1994 ko to darapọ mọ awọn oṣere.
Diẹ lara awọn ere ti Ogogo ti kopa ni 'Bolode O'ku', 'Apadi', 'Owo Blow', 'Obinrin So Wa Nu
Taiwo Hassan fẹ iyawo meji o si sabiyamọ ọmọ mẹrin.
4. Adebayo Salami- Oga Bello:

Oríṣun àwòrán, @Adebayo Salami
Agba ọjẹ ọṣere ni Adebayo Salami lati ipinle Kwara.
A bii ni ọjọ kẹsan an, oṣu karun un, ọdun 1952 nipinle Eko.
Lati kekere ni o ti bẹrẹ ere itage alarinjo nigba to darapọ mọ Young concert Party ti oloogbe Ojo duro Ladiipo.
To pada yi oruko pada si Awada kerikeri nigba ti Oga Bello di adari won leyin iku Ojo Ladiipo.
Ajani Ogun ni fiimu akọkọ to gbe Oga Bello sita ni eyi ti oun naa geb Ogun Ajaye sita.
O ti se ọpọlọpọ fiimu to si ti kopa ninu ogunlọgọ fiimu.
Awọn ọmọ rẹ naa si ti darapọ mọ ọ ninu iṣẹ ere itage bayii.
Lara wọn la ti ri: Femi Adebayo, Tope Adebayo ati bẹẹ bẹẹ lọ.
5. Yinka Quadri:

Oríṣun àwòrán, @Yinka Quadri
Yinka Quadri ti ọpọ n pe ni Kura jẹ agba oṣere.
O jẹ Oludari ere ati olootu ere sinima.
A bi Yinka Quadri ni ọjọ kẹfa, osu kẹsan an, ọdun 1959 ni agbegbe Lagos Island nipinle Eko.
O jẹ ọmọ ilu Oro nipinle Kwara. Oun naa ni Agbaakin ilẹ̀ Oro ni ipinle Kwara.
O lọ sile ẹkọ St Catholic School ni Idumagbo ati Christ High School ni Ebute Elefun nipinle Eko.
Odun 1976 ni Yinka Qudri bẹrẹ ere sise pẹlu awon ọrẹ rẹ kan bii Taiwo Olayinka eyi ti wọn pe orukọ rẹ ni Afopina Theatre Group.
Yinka Qudri kopa ninu ere olọsọọsẹ ati awọn ere onise mii bii Abulesowo, Bolode O ku, 'Apadi', 'Egbinrin Ote', 'Kutupu' ati béé béé lọ.
Yinak fẹ iyawo o si bimọ ati ọmọ ọmọ pẹlu awọn ọmọ ori itage to pọ.
6. Ganiu Nafiu: Alapinni:

Oríṣun àwòrán, @Alapinni Oosa
Ọpọ nkan nipa agbaọjẹ oṣere ni Ganiu Nafiu ti ọpọ mọ si Alapinni Oosa.
Ko si ẹni to le fidi ọjọ ori rẹ mulẹ nipato ṣugbon wọn gba pe o ti le ni ọgọrin ọdun.
O jẹ ẹlẹsin musulumi ṣugbon o ni imọ kikun nipa ẹsin abalaye.
Opo ololufẹ Alapinni Oosa ni wọn maa n gbadun ohun rẹ to yatọ.
O ti le logoji ọdun sẹyin to ti n ṣe ere itage kaakii.
Opo igba ni Rafiu Ganiyu maa n ṣe babalawo ninu ere Yoruba.
Saaju ko to maa ṣere lo ti kọkọ n ṣe awada kiri adugbo pẹlu awọn ọrẹ rẹ kan.
Lẹyin iku ọkan ninu wọn lo gba ile keu lọ ko to da ẹgbẹ tirẹ silẹ ni 1979.
O pada ba awọn agba ọjẹ oṣere bii Akin Ogungbe, Ray Eyiwumi ati awọn mii ṣere.
Ni Ipari, Awọn agba ọjẹ osere yii wa lara awọn to n mu itẹsiwaju ba agbo ere oniṣe Yoruba.
Ki ogo Yoruba maa tẹsiwaju lo wu awọn ololufẹ ede naa ninu iṣẹ akada ati lagbo idanilaraya.
- Kò dẹrùn láti ṣe fíìmù fún ìgbà àkọ́kọ́ láì sí ìyá mí níbẹ̀ - Ọmọ Iyabo Oko
- Ìtàn ayé Ọba Seriki Abass ti Badagry, tó ní aya 128, ọmọ 144
- Báwo ni èròjà Fáítámì D ṣe ń dáàbò bo àgọ́ ara wa?
- Wo àwùjọ kan tí àwọn obìnrin ti nílò láti fi ìwé ẹ̀rí àyẹ̀wò ìbálé wọn hàn nílé ọkọ
- Ṣé lóòtọ́ ni àwọn ọmọ ogun Naijiria àti Niger gba ogúnlọ́gọ̀ ìbọn lọ́wọ́ àwọn jàndùkú-
- Kà nípa àwọn Gomina míì tó tí fi agbára sọ́wọ́ ìgbákejì wọn lásìkò tí wọ́n lọ fún ìsinmi lẹ́nu iṣẹ́





















