Kidnapping on Lagos-Ibadan express: Àwọn 33 afurasí ajínigbé tó ń ṣọṣẹ́ ní òpópónà Eko sí Ibadan ti wà ní àhàmọ́ àjọ ọlọ́pàá

Oríṣun àwòrán, Others
Àjọ ọlọ́pàá ti nawọ́ gán àwọn afurasí gẹ́gẹ́ bí ajínigbé mẹ́tàlélọ́gbọ̀n tó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ oríṣìíríṣìí tán ń jí àwọn arìnrìnàjò gbé ní òpópónà márosẹ̀ Eko sí Ibadan. Ọlọ́pàá Oyo bẹ̀rẹ̀ kán lu ìgbó láti wá àwọn ajínigbé lópópónà Lagos-Ibadan Expressway
Àwọn afurasí ọ̀hún, tí àjọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Oyo nawọ́ gán, jẹ́ èyí tí àwọn afurasí ajínigbé tó ń ṣọṣẹ́ ní agbègbè Onigari níbi òpópónà márosẹ̀ náà níbi tí wọ́n ti jí àwọn kan tó ń lọ ibi ìgbéyàwó kan gbé láìpẹ́ yìí.
Kọmísọ́nnà àjọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Oyo, Ngozi Onadeko nígbà tó ń bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ lẹ́yìn tó ṣàfihàn wọn lánàá ní oríkò àjọ ọlọ́pàá tó wà ní Eleyele, Ibadan, ka orúkọ Aliu Umar, Isiaka Ibrahim àti Tambaya Usman lára àwọn tí wọ́n mú.
- ''Àwa ẹgbẹ́ Agbekoya ṣetán láti tú Sunday Igboho sílẹ̀ lẹ́wọ̀n pẹ̀lú agbára àwọn àgba''
- Àwọn aláṣẹ ilé ẹ̀kọ́ gíga Adekunle Ajasin sún ìdánwò tó yẹ kó wáyé lónìí síwájú, wọ́n ti iléẹ̀ka náà pa
- Buhari tako ọmọ bẹẹrẹ òṣì bẹẹrẹ ní Nàìjíríà, ó ṣàgbékalẹ̀ ètò láti dẹ́kun rẹ̀
- Ètò Ìsìnkú olóògbé Ernest Shonekan ti ń wáyé báyìí
- A kò fi ẹbí Timothy sílẹ̀, à ń gbiyànjú pé kí wọ́n dá ẹjọ́ náà padà sí Osun dípò Abuja ni- Agbẹjọ́rò Adekilekun
- Ẹ̀mí mọ́kànlá ló sọnù sí ìdìtẹ̀gbàjọba tó foríṣánpọ́n ní Guinea-Bissau
- Wàhálà tún bẹ́ sílẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ hìjábù ní Kwara, ìjọba ti iléẹ̀kọ́ Baptist ní Oyun pa
Onadeko sọ pé àwọn méjìlá nínú àwọn afurasí náà jẹ́ àwọn tó lọ́wọ́ nínú ìjínigbé tó wáyé ní Onigari, ìjọba ìbílẹ̀ Oluyole, lọ́nà márosẹ̀ Eko sí Ibadan.
Bákan náà ló tún ṣàfihàn àwọn afurasí ogún mìíràn fún ẹ̀sùn ìdigunjalè, ìpànìyàn àti ṣíṣe bí ọmọ ogun.
Báwo ni wọ́n ṣe mú àwọn ọ̀daràn náà?
Onadeko ṣàlàyé pé bí ìjínigbé ṣe ń fi gbogbo ìgbà wáyé ní òpópónà márosẹ̀ Eko sí Ibadan àti ìpànìyàn tó wáyé ní Onigari lọ́jọ́ keje, oṣù kìíní mú kí àwọn jí gìrì sí iṣẹ́ ní pẹrẹu.
Ónadeko ní akitiyan àwọn yìí ṣokùnfà kí àwọn nawọ́ gán afurasí kan tó ń jẹ́ Maku-Maku lọ́jọ́ kẹrìnlá, oṣu kìíní, à ti pé nígbà tí àwọn tún tẹ̀síwájú nínú ìwádìí àwọn ni àwọn nawọ́ gan àwọn yòókù.
Ónadeko fi kun un pé àwọn kan ti na pápá bora nínú àwọn afurasí gẹ́gẹ́ bí ọ̀daràn náà.
Onadeko ní àwọn afurasí náà ti jẹ́wọ́ pé àwọn ló wà nídìí ìjínigbé tó wáyé lọ́jọ́ keje, oṣù kìíní ní Onigari níbi tí Oluwatosin Anwajoye, 45, ti pàdánù ẹ̀mí rẹ̀.
- Àwọn ọmọ ogun America pa olórí ISIS, Ibrahim al-Qurayshi ní Syria
- Iná jó oko Obasanjo to wà ní ìpínlẹ Benue, Ẹbọra Òwu bínú, Ortom ni kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìwádìí ní kíá
- Inú wa kò dùn bí ó ṣe sọ̀rọ̀ tẹ́lẹ̀, lọ kọ́ síi nípa ọ̀rọ̀ tútù gẹ́gẹ́ bíi 'Ambassador'
- Ìjọba Kano fẹ̀sùn oníkókó márùn ún kan àwọn afurasí tó pa ọmọ ọdún márùn ún Hanifa
- Jide Kosoko, Otunba Dodoede n selédè lẹ́yìn Tafa Oloyede tó kú
- Oògùn olóró tó lé ní mílíọ̀nù kan la rí gbà lọ́wọ́ àwọn awakọ̀ Onitsha sí Kano- Àjọ NDLEA















