Adewale Elesho: Ìdí rèé tí ǹ kò ṣe sí nínú eré àgbéléwò mọ́

Oríṣun àwòrán, Adewale Elesho Adeoye
Adewale Adeoye, ti ọpọ awọn ololufẹ rẹ mọ si Adewale Elesho jẹ ọkan lara awọn agba ọjẹ ninu iṣẹ tiata Yoruba ti irawọ rẹ tan kaakiri agbaye.
Amọ ọpọ awọn eeyan lo n ṣakiyesi pe o ti tọ ọjọ mẹta ti awọn ti foju ganni rẹ kẹyin ninu ere.
Ninu ifọrọwerọ kan pẹlu awọn akọroyin, agba oṣere naa ṣalaye bi ọrọ ọhun ṣe jẹ.
- Àlàyé rèé lórí àìsàn tó ṣe mi fọ́dún mẹ́jọ tí mo fi rù kan eegun - Ogogo
- Fathia Balogun kéde aṣọ ẹbí ₦150,000 àti ₦120,000 fún ọjọ́ ìbí rẹ̀
- Dókítà àti Nọ́ọ̀sì di atọrọjẹ torí àjẹsílẹ̀ owọ oṣù mẹ́jọ
- Òkú kú ní ẹ̀ẹ̀kejì nígbà tí òkú 400 jóná ráúráú ní mọ́ṣúárì, ẹbí bú sẹ́kún lẹ́ẹ̀kejì
- Bí ayẹyẹ ìsìnkú Alao Akala yóò ṣe lọ rèé
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ pásítọ̀ tó ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ìyá àti ọmọ méjì
- Ọmọ Nàíjíríà, ẹ yé yan àwọn ‘Grandpa’ ní ààrẹ, ẹ wá ọlọ́gbọ́n ọ̀dọ́ tó tún sán-an-gun - Seyi Makinde
- Òjòwú-bìnrin fi ẹ̀rọ ìlọṣọ gbígbónà jó ọkọ ní abẹ́ àti ojú láti ojú oorun, ó sì gba ibẹ̀ kú
- Omijé lójú, ọ̀rọ̀ ìdárò àti orin èpè ní ọ̀dọ́ Eruwa fi dárò ikú bí Timothy Adegoke ti yóò wọ ilẹ̀ sùn lónìí
- "Á lọ yíká gbogbo ilẹ̀ Yorùbá láti bèèrè fún ìdáǹdè Sunday Igboho"
- Sanwo-Olu kède iye tí àwọn aráàlú yóò máa wọ ọkọ̀ ojú irin ayára bí àṣá tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ́ rà
O ni "Ọpọ eeyan lo ti n bere ibere yii lọwọ mi lẹnu ọjọ mẹta yii."
"Ti ẹ ba ṣakiyesi, ẹ oo ri pe ọpọ awọn ti a jọ jẹ sawawu ni ẹ ko fi bẹẹ ri ninu fiimu mọ, idi ni pe ọkan wa ko bale lori irufẹ awọn itan ti awọn ọmọ aye ode oni n kọ jade."
"Koda ninu ile emi funra mi gan, mi o le wo ọpọ ninu awọn ere ti wọn n gbe jade mọ nitori ko ni ọgbọn kankan ninu."
"Pupọ ninu awọn oṣerebinrin ni kii wọ aṣọ to bojumu, amọ wọn ko gbọrọ si wa lẹnu nitori pe awa kọ ni baba wọn."
Elesho tẹsiwaju pe "Ẹ ko le maa reti ki ẹni ti awọn obi rẹ gan ko gbadun lati maa wu iwa ọmọluabi."
Agba oṣere apanilẹrin naa ṣo siwaju si pe bi awọn kọlọrọsi kan ṣe maa n ṣe ẹda awo sinima tun n ṣakoba fun ere tiata ni Naijiria.
O ni "Ọpọ ninu wa lo maa ya owo ni banki lati fi ya fiimu, ṣugbọn lẹyinorẹyin, a kii jere lori rẹ."
"Akoko kan wa ti mo ka ẹnikan to ta ẹda fiimu ti mo gbe jade, amọ niṣe lo tun n halẹ mọ mi pe oun yoo fi oju mi ri mabo ti mo ba fi ọlọpaa gbe oun."
"A nilo ki ijọba ba wa da si ọrọ naa."
Ta ni Adewale Elesho?
Adewale Elesho jẹ ọkan lara awọn oṣere tiata Yoruba to dantọ ti irawọ rẹ si kan kaakiri agbaye.
Wọn bii lọjọ kẹwaa, ọsu Kinni, ọdun 1959 niluu Ikirun, ni ipinlẹ osun.
Ounnni Aarẹ ẹgbẹ oṣere tiata, igun ANTP.
Irawọ rẹ bẹrẹ si n tan lẹyin to kopa ninu ere "Taxi Driver" ti wọn gbe jade lọdun 1983.
Lara awọn tiata mii ti Elesho ti kopa to milẹ titi ni "Alaaru, Arike Osha, Oga Kan, Farugbotayin," ati bẹẹ bẹẹ lọ.



















