EndSARS Protest Update: Sowore ní ikọ̀ ọlọ́pàá yìnbọn fún òun lọ́jọ́ Ajé

Oríṣun àwòrán, @YeleSowore
Oludije fun ipo aarẹ Naijiria ninu eto idibo gbogboogbo to waye lọdun 2019, Omoyele Sowore, ti pariwo sita lori ayelujara pe, awọn kan n lepa ẹmi oun.
Ninu ọrọ kan to kọ si oju opo twitter rẹ ni alẹ Ọjọru lo ti sọ pe, oun ri iroyin gbọ pe ileeṣẹ eleto abo ni Naijiria ti kede pe, wọn gbọdọ mu oun tabi pa oun laarin wakati mẹrinlelogun si asiko yii, nitori pe oun ko ni gba ki wọn fi ofin gbe oun.
O ni olu ileeṣẹ ologun nilu Abuja, ni igbesẹ naa ti fẹ ẹ waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Bí nǹkan bá ṣe mí àtàwọn ọmọ mi, Aláàfin ni kẹ mú o - Olorì Anu figbe ta
- Ọ̀pọ̀ òkú fọ́nkálẹ̀ nílé ìwòsàn ìjọba ní Ore, ìpayà àjàkálẹ̀ àrùn gbàlú kan
- Ìpinu Gómínà láti dẹ́kun owó ìfẹ̀yìntì fáwọ̀n Gọ́mìnà àná dùn mọ́mi- Bola Ahmed Tinubu
- Ọkùnrin tó ṣe òfegè fọ́nran àwòrán ìgbéyàwó Buhari pẹ̀lú Mínísítà d'èrò ilé ẹjọ́
- Ṣé lóòtọ́ ni olorì méjì míì tún ti kúrò láàfin Oyo?
- Sọ́jà nà mí, tí mí mọ́lé bí wọn ti ṣe fún bàbá mi láyé ìjọba ológun Buhari - Ọmọ́ Busari Adelakun
"A mọ ki ẹ mọ pe eyi ko ni i di ijagbara fun ominira lọwọ."

Oríṣun àwòrán, @YeleSowore
O fikun pe ikọ ọlọpaa to wa nile asofin apapọ ilẹ wa sina ibọn fun oun lọjọ Aje, ti wọn si tun ji ọkan lara ọkọ ayọkẹlẹ oun lọ.
O ni wọn fi aake kọri lati da ọkọ naa pada lai naani pe oun fi n sisẹ iroyin ni, ti Kọmisana ọlọpaa nilu Abuja, Bala Ciroma si sọ fun oun pe ọkọ naa huwa ọdaran ni, ti wọn yoo si gbe lọ sile ẹjọ eyi to ba oun lojiji.
"Laarin ọsẹ kan pere, awọn alatilẹyin wọn kọ oniruuru atẹjade sita, wọn kọwe sawọn ileesẹ asoju ilẹ okeere lorisirisi.

Oríṣun àwòrán, @YeleSowore
Koda, ileesẹ itẹwe The Nation gan ni awọn ojulowo oluwọde EndSARs fẹ ki wọn ti mi mọle, ti ileesẹ ologun gan si ni awọn alasọdun loju opo Twitter, ti wọn n kede pe pipa lo yẹ ki wọn pa mi."
Sowore wa figbe bọnu pe, iditẹ mọ oun ti doju rẹ bayii lati bii ọsẹ diẹ sẹyin, ti wọn si ti ransẹ sawọn ileesẹ agbofinro, eyi ti asiri rẹ tu si oun lọwọ.
O ni eyi ko sẹyin ijọba aarẹ Muhammadu Buhari, ẹni to ti n dunkooko mọ oun lati ọsẹ diẹ, paapa lati igba ti iwọde EndSARS ti bẹrẹ.
Agbẹjọ́ro ọ̀dọ́ sọ́rọ́ ilẹ̀ kún nìjókòó ìgbìmọ̀ tó ń ṣe ìwádìí
Ọkan lara awọn ti banki apapọ Naijiria, CBN, gbẹsẹ le apo asunwọn wọn nile ifowopamọ, Adegoke Pamilerin, sọ pe o ti le ni ọsẹ meji ti oun ko ti le ṣe ohunkohun lori apo asunwọn wọn.
Ninu ọrọ kan to kọ sori ayelujara Twitter, o ni ṣaaju aṣẹ ile ẹjọ ni wọn ti gbẹsẹ le apo asunwọn naa.
Ọjọ Ẹti ni ile ẹjọ giga ijọba apapọ to wa nilu Abuja paṣẹ pe ki banki naa gbẹsẹ le apo asunwọn eeyan mọkandinlogin ati ileesẹ kan, fun ipa ti wọn ko ninu iwọde ENDSARS to waye l'oṣu Kẹwaa.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ile ẹjọ paṣẹ fun CBN lati gbẹsẹ le e titi di oṣu Kinni, ọdun 2021.
Gẹgẹ bi akọsilẹ idajọ naa ṣe fihan, Onidajọ Ahmed Mohammed lo fun CBN ni aṣẹ naa, ogunjọ oṣu Kẹwaa, si ni banki apapọ ọhun gbe iwe ẹbẹ lọ sile ẹjọ.
Oṣu to kọja ni iwọde #ENDSARS waye ni awọn ipinlẹ kan ni Naijiria, ati nilẹ okeere, eyi to mi ilẹ jakejado.
Iwọde naa ni ọpọlọpọ ọdọ ni Naijiria fi polongo fun fifi ofin de ẹka ileeṣẹ ọlọpaa to n gbogun ti iwa idigunjale, Special Anti-Robbery Squard, SARS.
Awọn ẹsun ifiyajẹni, ipaniyan, ati iwa ilọnilọwọ gba ni wọn fi kan awọn ọlọpaa SARS.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Iwọde naa ti kọkọ n lọ ni irọwọ-rọsẹ, ko to o dipe awọn janduku ja a gba kaakiri awọn ipinlẹ to ti n waye.
Koda, wọn dana sun awọn ileeṣẹ ọlọpaa, ile itaja, ati ọkọ ni awọn ipinlẹ bi Oyo, Eko, ati bẹẹbẹẹ lọ.
Awọn kan lara wọn si tun ko awọn oniṣowo ni ẹru lọ lẹyin ti ijọba kede konile-o-gbele.
Awọn ti banki apapọ gbẹsẹ le apo aṣunwọn wọn niyii:
•Bolatito Rachael Oduala
•Chima David Ibebunjoh
•Mary Doose Kpengwa
•Gatefield Nigeria Limited
•Saadat Temitope Bibi
•Bassey Victor Israel
•Wisdom Busaosowo Obi
•Nicholas Ikhalea Osazele
•Ebere Idibie
•Akintomide Lanre Yusuf
•Uhuo Ezenwanyi Promise
•Mosopefoluwa Odeseye
•Adegoke Pamilerin Emmanuel
•Umoh Grace Ekanem
•Babatunde Victor Segun
•Mulu Louis Teghenan
•Mary Oshifowora
•Winifred Akpevweoghene Jacob
•Victor Solomon
•Idunu A. Williams
Kini aṣẹ ile ẹjọ sọ lori apo asunwọn wọn?
Ile ẹjọ paṣẹ fun awọn banki pe ko gbọdọ si sisan owo wọle tabi gbigba owo jade ninu apo asunwọn ogun to wa ninu iwe ẹbẹ ti CBN kọ sile ẹjọ.
Ọgọsan ọjọ si ni awọn eeyan naa ko fi ni i ni anfaani si apo asunwọn wọn, titi CBN yoo fi pari iwadii ati ayẹwo to n ṣe.
- Mo ṣetán láti dojú ìjà kọ ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ bá ọ̀rọ̀ ajé Eko jẹ́- Sanwo Olu
- Wo ìgbà márùn ún tí Buhari ti rìnrin àjò lọ sókè òkun fún ìtọ́jú ara rẹ̀
- Bí àwọn kan tí ń ní àtimọ̀lé tí wọ́n sọ olorin Nazir sí ní Kano ni ọwọ́ kan òṣèlù ní àwọn mii ní...
- Wo àwọn ọmọ Naijiria mẹ́ta tó jáwé olúborí nínú ìdìbò sílé aṣòfin ilẹ̀ Amẹrika
Awọn banki bi i of Access, Fidelity, First Bank Nigeria, Guaranty Trust Bank, United Bank of Africa, ati Zenith, ni ile ẹjọ fi iwe aṣẹ ranṣẹ si i.
O si tun sun igbẹjọ lori ọrọ naa si ọjọ kẹrin, oṣu Keji, ọdun 2021.
Bakan naa lo sọ pe ẹnikẹni ti aṣẹ naa ba bawi, le kọwe sile ẹjọ lati gbọ awijare rẹ.















