Ibrahim Babangida: Buhari ní Nàìjíríà kò lè gbàgbé iṣẹ́ ribiribi tí IBB ṣe láéláé bí ó ti pé ẹni ọdún 79 lónìí

Oríṣun àwòrán, Twitter/Presidency
Aarẹ Muhammadu Buhari ti ki olori orilẹede Naijiria nigba kan ri, ajagun fẹyinti Ibrahim Badamosi Babangida ku ọjọ ibi ọdun kọkandinlọgọrin lonii ọjọ kẹtadinlogun oṣu kẹjọ.
Ninu atẹjade kan ti oludamọran aarẹ lori ọrọ iroyin, Femi Adesina fi sita loju opo Facebook rẹ, Buhari ni titi laelae ni orilẹede Naijiria yoo maa ṣe iranti iṣẹ ribiribi ti Babangida ṣe, nigba to fi wa lori aleefa.
- Nǹkan wọ̀lú! Afurasí ikú ọ̀wọọ̀wọ́ l'Akinyele jápa mọ́ ọlọ́pàá lọ́wọ́
- Kí ló mú Obasanjo ti ilẹ̀kùn mọ́ ẹbí, òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ ní ibi òkú àna rẹ̀?
- Emir Ilorin fẹ́ parí ìjà Risikat olójú búlúù àti ọkọ rẹ̀
- Wo ọmọ Nàíjíríà tí wọn fi pósí ‘₦34m’ sin
- Yéèpà, òfin ìtakété síra ẹni forí ṣánpọ́n lásìkò ọdún Osun Osogbo
- Ẹ fura, iyọ̀ onímájèlé tó dóde ti gbẹ̀mí èèyàn méje!
- Àlá àwọn òjíṣẹ́ Olúwa tó fẹ́ jẹ ààrẹ Nàíjíríà leè má ṣẹ lógún ọdún - Abiara
Aarẹ Buhari wa gbadura pe ki Eleduwa tubọ fi okun, ilera to peye ati ẹmi gigun jinki olori orilẹede Naijiria tẹlẹ ri.
Bakan naa ni aarẹ ana orilẹede Naijiria, Gooluck Jonathan ṣe ṣadankata IBB, bi o ti pe ọdun mọkadinlọgọrin loke eepẹ.
Jonathan ni lai ṣe ani ani, Babangida ko ipa ribiribi ninu idagbasoke orilẹede Naijiria.
Jonathan wa gboṣuba rabandẹ fun IBB fun ifẹ nla to ni si Naijiria ati ipa rẹ lati rii pe orilẹede yii wa ni iṣọkan.
Jonathan tun gbadura ilera, alaafia ati ayọ fun Babangida bi o ti n sun mọ bebe ọgọrin ọdun.

Oríṣun àwòrán, Others
Ajagun fẹyinti Babangida jẹ aarẹ ologun orilẹede Naijiria laarin ọdun 1985 si 1993.
IBB tẹ ń pariwo pé ó kú, kò kú o, Ko ko lara ọta ń le- Agbẹnusọ Kassim
Bi ẹ ba ri bi Ọgagun Ibrahim Babangida ṣe n ṣe kébékébé pẹlu okun ara to dara lonii.
Ọpọlọpọ iroyin lo bẹrẹ si ni tan an kalẹ lonii wi pe IBB ti dagbere faye lowurọ oni ko da titi dori oju opo aṣewadi iroyin lagbaaye Wikipedia gan.

Oríṣun àwòrán, Getty Images, Wikipedia
Ẹwẹ, agbẹnusọ ọgagun Babangida, Ọmọba Kassim Sule sọ fun BBC Yoruba wi pe bẹẹ naa lawọn ṣe ji lowurọ yii ti awọn n gbọ iroyin ẹlẹjẹ ọhun kaakiri.
O ni gbigbọ iroyin naa pa awọn lẹrin gidi gan, "o ya ni lẹnu ko si si ibọwọ fun ni kankan ninu iroyin naa".
Kassim ni ki awọn oniroyin ma baa ṣi awọn eniyan lọkan, oun ni lati fi ọrọ sita lati bu nu atẹ lu iroyin ofege yii pe irọ gbaa ni ohun ti wn n gbe kiri tori Babangida ko tii ku.

"Kẹẹ si maa wo o, ni nkan bii ago mejila ọsan kọja iṣẹju mẹwaa ni IBB jade wa lati wa bẹrẹ si ni yọju si awọn alejo rẹ.
- Àìsàn tó ń ṣe mí kìí ṣojú lásán! Àdúrà ni mo nílò kìí ṣowó - Pa Kasumu
- Ọlọ́pàá fi pampẹ́ òfin mú Duncan Mighty lórí ẹ̀sùn jìbìtì mílíọ̀nù mọ́kànlá
- 'Penis Fish,' ẹ̀ja tuntun tó rí bí nǹkan ọmọkùnrin lúwẹ̀ẹ́ jáde nínú òkun
- Kamaru Usman, Ọmọ Naijiria f'ẹ̀ṣẹ́ gba ìgbànú ẹ̀yẹ mọ́ Covington lọ́wọ́ ní ìdíje UFC
- Ọ̀jọ̀gbọ́n fásitì OAU pàdánù ẹ̀mí lópoópónà Benin sí Auchi.
Ipo wo gan ni ilera Gbadamọsi Babangida wa lọwọlọwọ?
Nigba ti akọroyin BBC bere pe bawo gan an ni ilera ọgagun Babangida ṣe wa ni lọọlọ yii, agbẹnusọ rẹ fesi pe "ko ko ko lara ọta baba n le".
O ṣalaye pe ẹsẹ ti ọgagun Ibrahim Babangida fi pa lasiko ogun abẹle Naijiria nikan lo ṣi n dun un ṣugbọn eyi kan kun ọjọ ogbo lasan ni".
Kassim ni yatọ si eleyi, o ṣi n gun ori akasọ lọ sun si yara rẹ o si n sọkalẹ wa funrarẹ.
O ni o yani lẹnu iru iroyin ti awọn ileeṣẹ iroyin Naijiria maa n gbe kiri.
"Ko sohun to n jẹ pe o sun ko ji mọ o, ko sohun to n jẹ o sun o rẹ ara. Ojoojumọ lo n jade wa yọju si awọn eeyan".
"Bi ẹyin naa ba wa pẹlu rẹ bi a ṣe n sọrọ yii, yoo ya yin lẹnu bi ara rẹ ṣe le ko ko ko".















