2023 Election: Wike ní àwọn agbésùnmọ̀mí ru igi oyin tí òun bá dí ààrẹ Naijiria

Gomina Nyesom Wike

Oríṣun àwòrán, Facebook/Rivers State Government

Gomina ipinlẹ Rivers, Nyesom Wike ti ni awọn agbebọn ati agbesunmọmi ti ru igi oyin ni kete ti oun ba ti di aarẹ lorilẹede Naijiria.

Wike sọ eyi lasiko to n jiroro pẹlu awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP lati ipinlẹ Taraba lori igbiyanju rẹ lati dije dupo aarẹ ni ọdun 2023.

O ni iṣoro ti ẹgbẹ oṣelu PDP gbọdọ koju ni lati ri pe eto aabo Naijiria ni ojutu ki eto aabo le lojutu.

''Ohun to damiloju ni pe ti awọn agbebọn ba gbọ orukọ mi wọn ma sare kabakaba fun ẹmi wọn nitori mi o ni gba fun wọn.''

''Ma a ri pe mo ṣiṣẹ bi adari ikọ ọlọgun lorilẹede Naijiria''

Wike

Oríṣun àwòrán, Google

Wike fikun un pe oun yoo sa gbogbo ipa oun lati ri pe inu awọn ọmọ Naijiria dun.

Bakan naa ni lati oun yoo ri pe itẹsiwaju wa ni ẹka eto agbẹ, eto aabo, ati eto ọrọ aje ni Naijiria.

"100m tí APC ń bèrè fún owó fọ́ọ̀mù kò ní jẹ́ kí àwọn tó nífẹ́ aráàlù dé ipò ìjọba"

Onimọ nipa ọrọ oṣelu kan, to tun ti fi igba kan du ipo gomina ni ipinlẹ Ondo, Dotun Ojon ti sọ pe awọn to ni ọpọlọ ko ni lanfaani lati dije du ipo Aarẹ ni Naijiria mọ ni bayii ti awọn ẹgbẹ oṣelu n kede ẹgbẹlẹgbẹ miliọnu naira gẹgẹ bii owo fọọmu.

APC

Oríṣun àwòrán, @tweetfm74

Ọrọ yii lo n jade lẹyin ti ẹgbẹ oṣelu APC kede ọgọrun miliọnu naira gẹgẹ bii owo fọọmu fun ẹnikẹni to ba nifẹ lati du ipo Aarẹ, ati aadọta miliọnu naira fun ẹni to ba nifẹ lati du ipo gomina ninu ẹgbẹ oṣẹlu naa.

Ojon sọ fun BBC Yoruba pe lootọ, awọn ẹgbẹ oṣelu nilo ọpọlọpọ owo lati gbe ẹru ẹgbẹ naa, amọ iye owo ti ẹgbẹ APC kede yii kọja ojuẹ.

Gẹgẹ bii ohun to sọ "Eyii tumọ si pe awọn to ni ọpọlọ, atawọn to ni ọkan lati ṣiṣẹ fun awọn eeyan, o ṣeeṣe ki wọn ma le ri irufẹ awọn owo ti awọn ẹgbẹ oṣelu wọnyii n bere fun ko silẹ."

"Eyii yoo mu ko ṣoro fun awọn to ba le ṣiṣẹ daadaa amọ ti wọn ko ni owo lati ri anfaani lati de ipo ijọba."

"Ti ẹ ba woo daadaa, ẹni to jẹ ogoji ọdun, to ni ifẹ araalu lọkan to si ja fafa, amọ nibo lo ti fẹ ri iru owo to fẹ fi gba fọọmu ti a n sọ yii?"

Àkọlé fídíò, Ọdún 20 ni ìran ti jáde pé kí n di ààrẹ!'Wàláhì láàrín ọdún kan péré tí mo bá dé Aso Rock, ẹ wo ǹkan tí ...'

Ṣe lootọ ni APC fẹ yọ ọwọ awọn kan kuro lawo eto idibo ọdun 2023?

Ninu erongba Ojon, iye owo fọọmu ti APC kede kii ṣe ọna lati yọ ọwọ awọn oludije kan kuro lawo eto idibo ọdun 2023.

O ṣalaye pe gbogbo awọn to ti fi erongba wọn lede lo koju oṣuwọn lati gba fọọmu naa, amọ ẹgbẹ oṣelu APC kan n wa owo ni.

Ojon ni "APC kan n wa owo ni, ati pe wọn tun fi owo fọọmu naa sọ pe awọn lo wa ni ijọba ati pe wọn ko si ni kilaasi awọn ẹgbẹ oṣelu yoku."

Dotun Ojon sọ siwaju pe kii ṣe APC nikan lo n ṣe irufẹ nnkan bayii, gbogbo ẹgbẹ oṣelu to ba ti wa ni ijọba lo maa n kede owo fọọmu gọbọi, amọ ko daa to.

Àkọlé fídíò, 'Fásitì Nàìjíríà kò gbà mi wọlé ló mú mi sá lọ Ukraine, àmọ́ ohun tí ojú mi rí nínú ogun náà rèé kí ń tó sá wá Nàìjíríà'

Ohun ti awọn araalu le ṣe

Ojon woye pe kaka ki awọn araalu tabi ki oloṣelu maa fapa janu lori iye owo ti APC kede, wọn le dẹyin lẹyin APC ki wọn si ba ẹgbẹ mii lọ.

O ni "Kii ṣe ẹgbẹ oṣelu APC ati PDP nikan lo wa ni Naijiria, awọn eeyan lọ si ẹgbẹ mii."

"Ti awọn araalu yin ba wa lẹyin yin, ẹ ko nilo lati wa ninu ẹgbẹ oṣelu ti wọn yoo ti maa bere N100m lọwọ yin, ẹ le lọ sinu ẹgbẹ mii."

"Nitori ọgọrun miliọnu naira owo fọọmu ti APC n bere fun yii to fun awọn ẹlomiran lati da ẹgbẹ oṣẹlu silẹ, ki wọn si ṣe awọn ilana to yẹ ninu naa ko le ni gbongbo."

Àkọlé fídíò, Wọ́n jí pè mi láàrọ̀ pé ọmọ mi bímọ, ó dákú àmọ́ bí mo ṣe débẹ̀, àt'òkú ọmọ mi, àt'òkú