El-Adonai Evangelical Ministry: Iná ìjọba gbé àwọn olújọ́sìn nínú ṣọ́ọ̀ṣì lásìkò ìsìn ní Ọjọ́ Ìsinmi

El-Adonai Evangelical Ministry

Oríṣun àwòrán, Others

O kere tan olujọsin mẹfa ni ina gbe ni ijọ El-Adonai Evangelical Ministry, ni agbegbe Abule Egba, nipinlẹ Eko.

Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn ni waya opo ina lo dede jabọ si ori orule ile ijọsin naa lasiko ti wọn n ṣe isin lọwọ ni owurọ Ọjọ Aiku.

Ohun to fa iṣẹlẹ naa ni pe ami idanimọ ile ijọsin naa kan opo ina to wa nibẹ, eleyii to fa ki ina gbe orule ijọ naa.

Amọ ile ijọsin naa ko i tii fi orukọ awọn to lugbadi ijamba naa lede, ti wọn si ti wa ni ileewosan amọ ti wọn ko mọ ara nigba ti awọn oniroyin kan si awọn alaṣe lori iṣẹlẹ naa.

Awọn ti iroyin naa ṣẹlẹ loju wọn awọn mẹrin ku ninu awọn mẹfa ti iṣẹlẹ ina naa gbe. ti awọn meji to ku si wa ni ẹṣẹ kan aye, ẹṣẹ kan ọrun.

''A wa ninu ile nigba ti iṣẹlẹ naa waye ni nkan bi aago meje ni owurọ ọjọ isinmi.''

''A koko ro pe gaasi lo fa ina naa nitori ile ijọsin naa fẹ ṣẹ ayẹyẹ idupẹ ni aarọ ọjọ naa.''

''Nigba ti a jade lari pe asia ṣọọsi naa kan waya opo ina lo jẹ ina gbe awọn to wa ni abẹ rẹ. Ti awọn mẹrin ninu wọn si ku, ọdọlangba meji ati awọn ogo wẹẹrẹ meji.''

El-Adonai Evangelical Ministry

Oríṣun àwòrán, Others

''O ṣeeni laanu pe iṣẹlẹ yii fa rudurudu ni agbegbe naa ti pasitọ ijọ naa si salọ, ki awọn ọdọ adugbo naa to lọ jo ṣọọṣi naa ati gbogbo ohun to wa nibẹ.''

''Ọpẹlọpẹ awọn ọlọpaa to wa nibẹ lo jẹ ko rọlẹ, ti awọn eniyan si pejọ lati salaye bi nkan ṣe ṣẹlẹ ni agbegbe naa.''

Ọkan lara awọn ti ọfọ naa ṣe ni ọmọ ka ni oun mọ, oun ko ba ti jẹ ki ọmọ naa tete lọ si ileejọsin ni ọjọ naa nitori nigba to ji lo sọ wi pe oun fẹ lọ tun ṣọọṣi ṣe.

Iroyin ni ileeṣẹ panapana Lagos Fire Service ni wọn pe lati tete doola ẹmi awọn eniyan ki o to gbina to si le gbemi awọn eniyan tabi ba dukia jẹ.

Àkọlé fídíò, Ebun Oloyede Olaiya Igwe sọ ohun tí ojú rẹ̀ rí lásìkò àìsàn kídìnrín tó yọ ọ́ lẹ́nu

''A ti fi to ileeṣẹ to n pin ina ka nipinlẹ Eko, Ikeja Electric Distribution Company ti wọn si ti pa gbogbo ina ni agbegbe naa, eleyii ti yoo doola ẹmi awọn eniyan ni agbegbe naa.''.

Àkọlé fídíò, Akomolede: Akuko Gagara ni ìwé tó ṣàfìhàn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ní Nàìjíríà lásìkò yìí- Fatimo B

Ileeṣẹ ọlọpaa ti ni iwadii ti bẹrẹ lori iṣẹlẹ naa bi o tilẹ jẹpe ohun ti awọn ri fihan pe kii ṣe pe awọn eniyan mọọmọ jẹ ki ina gbe awọn eniyan.

Àkọlé fídíò, 'Ìyà Muinat kú nígbà tó ń mu ọmú lọ́wọ́ ni èmí ìyà-ìyá rẹ̀ ń tọ́jú rẹ̀ kí ògiri kíláàsì tó wó pa á'