Lagos Yoruba Nation Rally: Femi Falana ní ètò tí Ọlọ́pàá ti ṣe sílẹ̀ ló fa ikú ọmọ ọdún mẹ́rìnlá náà

Oríṣun àwòrán, Others
Agbẹjọro agba ati ajafẹtọ ọmọniyan, Femi Falana ti sọrọ lori iṣẹlẹ to waye ni Ọjọta lasiko iwode Yoruba Nation to mu ẹmi ọmọ odun mẹrinla lọ lasiko iṣẹlẹ naa.
Femi Falana ni awọn ọlọpaa ko ṣeeṣi yin ibọn lu ọmọbinrin ti orukọ rẹ n jẹ Jumoke naa, amọ wọn ti ro ninu ara wọn tẹlẹ wi pe awọn yoo pa eniyan lasiko iwọde ọhun.
Amọ ileeṣẹ ọlọpaa ni ọta ibọn awọn kọ lo pa Jumoke nitori awọn ko yinbọn lasiko iwọde Yoruba Rally to waye ni ilu Eko.
- Sunday Igboho kọ̀wé sí ìjọba àpapọ̀, o ní dandan kí wọn sàn owó gbà má bínú ₦500m
- ''Ṣọ́ọ̀bù ìyá rẹ̀ ní Jumoke wá tí ìbọn ọlọ́pàá ti pa lásìkò ìwọ́de Yoruba Nation ní Ojota''
- Àyẹ̀wò tí a ṣe fihàn pé kìí ṣe òkú tútú ni ọmọ tí wọ́n sọ pé a pa ní Ojota - Ọlọ́pàá Eko
- Gbogbo ìpilẹ̀sẹ̀ ìṣoro Nàìjíríà ni àtúnyẹ̀wò òfin ta ń ṣe yìí yóò mójútó - Gbajabiamila
- Ẹ má gbàgbé láti mú "Candle" yín wá síbi ètò ìsínkú Wòlíì TB Joshua tí yóò bẹ̀rẹ̀ lọ́la - Ìjọ SCOAN
Falana lasiko to n ba ileeṣẹ iroyin Sunday Punch sọrọ ni ileeṣẹ ọlọpaa doju ofin orilẹede Naijiria bolẹ ni Section 83 (4), nitori awọn ọlọpaa lo yẹ ko pese aabo fun awọn araalu.
O ni awọn ọlọpaa yẹ ko pese aabo fun awọn to n ṣe iwọde ni ọwọọwọ lai si wahala, amọ niṣe ni ọlọpaa tu wọn ka ni ọna aitọ.
Agbẹjọrọ agba naa ni ileeṣẹ ọlọpaa n parọ ni pe awọn kọ lo pa ọmọ naa lati da abo bo ẹni to ṣiṣẹ ibi ọhun laarin wọn.
''Nitori awọn ọlọpaa le awọn oluwọde naa lọna aitọ fihan pe wọn mọọmọ pa ọmọ ọdun mẹrinla naa.''
''O ṣeni laanu bi awọn ọlọpaa ṣe sare sọ wi pe awọn kọ ni wọn ṣiṣẹ ibi naa lai ṣewadii''
- Wo ohun tó yẹ kí o ṣe sí ojú abẹ́ rẹ, ''vagina'' lẹ́yìn ìbálòpọ̀
- "DSS yin ọta ìbọn 48 sí Adogan, kò sì kú, ni wọn bá fi ọmọ odó fọ lórí"
- Wo ohun tó yẹ ko mọ̀ nípa Saheed Adigun (Adogan) tó kú nílé Sunday Igboho
- Bí Igboho kò bá jáde, àwa yóò jáde fúnra wá, ìyà pọ̀ - Oluwọde Yoruba Nation
- Ṣé lóòtọ́ ni Sunday Igboho dé síbi ìwọ́dé Yoruba Nation l‘Eko?
- "DSS tó kọlu ilé Sunday Igboho dàbí pé wọ́n gbé ‘Map’ ilé náà lọ́wọ́ ni"
- Ìlérí ta ni yóò ṣẹ láàrin àwọ̀n olùwọ̀de Yoruba Nation àti ọlọ́pàá?
Bakan naa ni Femi Falana wa ke si ijọba ipinlẹ Eko lati ṣe ayẹwo ni ileewosan, iru iku to pa ọmọbinrin ọdun mẹrinla naa ni ibi iwọde Yoruba Nation.
Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn ni inu ṣọọbu iya rẹ ni Jumọke wa ti ibọn ti lọ ba ani ikun to si ku lojiji.













