IGP Adamu: Pẹsẹ́ ní Ọlọ́pàá Naijiria wà látàrí ìṣekúpani Ọ̀gágun Iran

Oríṣun àwòrán, OTHERS
Ọga ọlọpaa lorilẹ-ede Naijiria, Mohammed Adamu ti kesi ileeṣẹ ọlọpaa kaakiri lati wa ni pẹṣẹ lati koju ipenija kankan to ba yọju si wọn.
Eyi ko ṣẹyin bi Adamu sẹ fi lede wi pe o ṣeeṣe ki awọn ọlọlufẹ ọgagun orilẹ-ede Iran, Qassem Soleimani to wa labẹle fẹ da rogbodiyan silẹ, lẹyin ti orilẹ-ede Amerika ṣekupa ọgagun naa.
Ọga agba ọlọpaa naa fi lede ni oju opo ikansiraẹni Twitter lori iwadii ti iṣẹ ọtẹlẹmuyẹ gbe jade
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Opin ọsẹ yii ni orilẹ-ede Amerika fi ibugbamu oloro pa ọgagun naa lori ẹsun pe o ti pẹ ti ọgagun naa ti n wa nidi iṣekupani awọn ọmọ ilẹ Amerika.
- Ẹ wo àwòrán bí ọjà Akẹsan ṣe jóná ràùràù ní ìlú Oyo!
- Irú kí lèyì! Pásítọ̀ gún ìyàwó rẹ̀ lọ́bẹ nínú ṣọ́ọ̀ṣì, ló bá tì í bọ ara rẹ̀ náà níkùn
- Yoruba language: Ọdún 2020 to wọlẹ́ dé yìí á tu gbogbo wa lára
- Oyo Fire: Dukia ṣófo, ọmọ ọdún mẹ́rìnlá faragbọta níbí iná tó jó ọjà Akesan
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Simon Mallam wa nínú àwọn mẹ́fà tó ti kú nínú ìjàmbá iná gáàsì- Ìjọba Kaduna
Ọga ọlọpaa lorilẹ-ede Naijiria, Mohammed Adamu naa wa pasẹ fun kọmisọnna ọlọpaa ati awọn ọga ọlọpaa ni ẹkun kọọkan lati wa ni pẹsẹ lati koju awọn eniyan to ba fẹ fa rogbodiyan.
Bakan naa ni Adamu fi da awọn ara ilẹ okeere to wa ni Naijiria lati ma bẹru nitori nitori wi pe aabo to peye yoo wa fun wọn.










