Ọwọ́ tẹ afurasí ajínigbé ọmọ Yorùbá tó n pe ara rẹ̀ ní Fulani àti àwọn mẹ́fà mìí ní Ekiti

Oríṣun àwòrán, Ekiti state police
Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Ekiti ti ṣafihan ikọ afurasi ajinigbe kan ni olu ileeṣẹ ọlọpaa to wa nilu Ado Ekiti.
Agbẹnusọ ọlọpaa nipinlẹ naa, Sunday Abutu sọ fun awọn akọroyin pe meje ni awọn afurasi naa, ti ọkunrin kan to ti fi igba kan jẹ ọlọpaa ri, Ayo Samuel si wa.
Gẹgẹ bo sẹ sọ ọkunrin mẹfa, obinrin kan lo wa lara wọn.
Ọjọ kẹfa, oṣu Kọkanla, ni ọwọ kọkọ tẹ mẹrin lara wọn ki ọwọ to tun tẹ awọn mẹta yooku lọjọ kejidinlogun, oṣu Kọkanla nilu Ilorin,nipinlẹ Kwara.
- Àwọn ọlọ́pàá ti ń wá okùnrin tó gbé òkú ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ sínú fííjì lẹ́yìn tó gbẹ̀mí rẹ̀ tán
- "Lẹ́yìn ti mo lo ọdún 42 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, wọ́n tú mi sílẹ̀ pé ń kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn"
- Àlàyé ọlọ́pàá Osun rèé lórí ọ̀nà tí Rahmon Adedoyin gbà ká ọ̀rọ̀ rẹ̀ sínu fọ́nrán ohùn tó lu ayélujára pa
- Èèmọ̀! Bíṣọ́ọ́bù bá ọmọ tuntun lórí pẹpẹ ṣọ́ọ̀ṣì, láì mọ ẹni tó ni
- Jàndùkú kọlù mi, gé mi lára bíi olè torí mo jẹ́rìí tako ìjọba níbi ìwádìí ìpànìyàn Endsars Lekki''
Agbẹnusọ ọlọpaa sọ ninu atẹjade to fi sita pe wọn jẹwọ pe awọn lo ji ọkunrin kan, oloogbe Ayeni Abiodun gbe, amọ to bẹ jade ninu ọkọ wọn loju popo, to si pada ku nileewosan.

Oríṣun àwòrán, Ekiti state police
Bakan naa lo ni ẹnikan lara wọn, Johnson Apotire jẹwọ pe oun ma n dibọn bi Fulani darandaran nitori pe irisi rẹ jọ Fulani.
Ẹwẹ, Ọgbẹni Abutu sọ pe ajọṣepọ pẹlu ileeṣẹ ologun, Amotekun, NSCDC to fi mọ awọn ọlọdẹ ibilẹ, lo mu ki ọwọ tẹ wọn.








