You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Olufon ti Ifon Murder: Àwọn agbébọn tó pá Olufon ti Ifon ti ṣe ohun èèwọ̀ ní ilẹ̀ Yoruba
Awọn lọbalọba nipinlẹ Ondo ti ni ohun eewọ ni awọn agbebọn to ba Olufọn ti Ifọn, Oba Isreal Adeusi ṣe lẹyin ti yinbọn pa.
Awọn lọbalọba naa sọrọ gba ẹnu alaga awọn lọbalọba nipinlẹ Ondo, Ọba Frederick Akinruntan to jẹ Olugbo ti Ugbo.
Oba Akinruntan ṣe apejuwe iṣekupani Oba Adeusi gẹgẹ bi ohun to bani ninu jẹ, ti awọn si tako patapata.
- Akomolede ati Asa Yoruba: Kí ni "Present tense" lédè Yorùbá?
- Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ oṣù tí òjò kò rọ̀ ní orílẹ̀èdè Cuba, Ọba ilẹ̀ Yorùbá ló pàṣẹ kí òjò rọ̀ níbẹ́ tó sì rọ̀-Elebuibon
- Olorì Aláàfín tẹ́lẹ̀, Anuoluwapo Adeyemi gba àmì ẹ̀yẹ lórí ipa tó kó nínú oge ṣíṣe
- Ṣé àwọn ìjayà ajaguntà ilẹ̀ òkèrè leè bá Nàìjíríà fòpin sí ìṣòro àbò?
- Awakọ̀ agbókùú, ọlọ́pàá, ológun, oníròyìn ló máa ń kọ́kọ́ dìbò ní Ghana, bó ṣe ń lọ rèé
Oba Akinruntan ni iṣeeṣe awọn lọbalọba lorilẹede ko di atẹmẹrẹ nitori eto aabo to dẹnukọlẹ lorilẹede Naijiria.
Oba Olugbo ti Ugbo wa rọ Gomina Oluwarotimi Akeredolu lati lo gbogbo ohun to wa ni ikawọ rẹ lati gbogun ti awọn aṣekupani ni ipinlẹ Ondo.
O rọ Gomina Akeredolu lati pese eto aabo fun awọn lọbalọba lati ri wi pe iru iṣẹlẹ yii ko waye mọ.
Oba Akinruntan wa gbadura fun awọn iyawo, ẹbi ati ọrẹ ti Ọba Olufon fi silẹ, wi pe iru ibanujẹ bẹẹ ko ni kangun si wọn mọ.
Awọn agbebọn yinbọn lu Oba Adeusi ni agbegbe Elegbeka ni opopona Owo-Ifọn ni ipinlẹ Ondo.
Amọ, ẹpa ko boro mọ nitori nigba ti yoo fi de ileewosan ijọba ni Owo, Oba ti tẹri gbasọ.
Wo ohun tí Ọọ̀ni, Sultan Sokoto sọ nípa ọta ìbọn tó gbẹ̀mí Ọba Olúfọ́n
Awọn ọbalaye kanrinkanrin meji lorilẹede Naijiria ti bu ẹnu atẹ lu bi ọrọ abo ṣe dẹnukọlẹ lorilẹede Naijiria eyi to ṣokunfa iṣekupa ọbaalaye, Olufọn ti ilu Ifọn-Owo ni ipinlẹ Ondo.
Ọọniriṣa, Alayeluwa Adeyẹye Ogunwusi Ọjaja II ati Sultan ti ilu Sokoto, Sa'ad Abubakar kẹta ṣalaye pe ohun to banininu jẹ gidi ni pe awon avbenipa lee gba ẹmi ọbalaye lorilẹede Naijiria.
- Toyin Abraham fi orin yẹ́ Iyabo Ojo sí níbi ìsìnkú ìyá rẹ̀, Falz di ẹni tí wọ́n fí òpópónà ṣọ orí rẹ̀
- Ọkọ mi bẹ̀rẹ̀ sí ní lù mí lẹ́yìn tí mo lòdì sí ibálọ̀pọ̀ láti ihò ìdí lẹ́yìn- Sabira
- Wo bí ilé ìwòsàn LUTH ṣe ń gba owó ibùsùn lọ́wọ́ àwọn aláìsàn, tí àwọn míràn sì ń sun ìta
- 'Àwọn ọlọ́pàá ti bẹ́ síta láti ṣàwárí àwọn olè 30 tó jówó kó lọ ní Union Bank l'Ondo'
Nibi idanilẹkọ kan ti wọn fi sọri ayẹyẹ ọdun karun Ọọni Ogunwusi lori itẹ, eyi to waye nilu Ibadan ni wọn ti sọrọ yii.
Bakan naa ni wọn tun duro idakẹjẹ iṣẹju kan ni iranti Ọbaalaye naa, kabiyesi Olufọn ti ilu Ifọn-Ọwọ,
Àràbà nlá tó wó nípìnlẹ̀ Ondo jẹ́ ká mọ̀ pé inú ìpèníjà ètò ààbò tó kọjá ojú lásán la wà - Ìjọba ìpínlẹ̀ Ondo
Ijọba ipinlẹ Ondo ti kẹdun iṣẹlẹ to waye ni agbegbe Elegbeka, ni oju ọna Ifon si Owo.
Ninu atẹjade ti Kọmisanna fun eto iroyin ati ilanilọyẹ, Donald Ojogo, fi sita, o fidirẹ iṣẹlẹ sọ pe àràbà nla kan lo wo ninu iṣẹlẹ naa.
- Ọlọ́pàá dóòlà ẹ̀mí èèyàn 10 nínú àwọn 16 tí ajínigbépawó jí gbé l'Óǹdó
- Ìpínlẹ̀ Oyo, Ogun, Ondo buwọ́lu àbádòfin Àmọ̀tẹ́kùn
- Ṣé Fulani daran-daran ni àwọn tó n jí ènìyàn gbé ní ìpínlẹ̀ Ondo?
- Ọmọ ogún ọdún kan tún di àwátì nílùú Akurẹ nípìnlẹ́ Ondo- PPRO
- Ajínigbé méjé ni a ti fi ṣìkún òfin mú ní ìpínlẹ̀ Ondo - Amotekun
O ṣapejuwe iṣẹlẹ naa gẹgẹ bi ọgbẹ to wọ to jin, to si jẹ ibanujẹ.
Bo tilẹ jẹ pe ijọba ipinlẹ naa "yoo bọwọ fun aṣa ati iṣe ilu naa, ti ko si ni sọ nkankan nipa orukọ àràbà nla to wo nipinlẹ naa", iroyin to n lọ nipe Olufon ti Ifon, Ọba Isreal Adewusi ni awọn afurasi ajinigbe pa.
Bakan naa lo ni Gomina Rotimi Akeredolu, ati awọn olori ijọba kan ti ṣe abẹwo si agbegbe naa, lati ba wọn kẹdun.
Ijọba ipinlẹ Ondo sọ pe iṣẹlẹ naa tọka si pe ipenija eto aabo to kọja oju lasan, lo n ba 'wa' finra.
"Eyi to si n pe fun igbesẹ to tayọ."
Alẹ Ọjọbọ ni iroyin naa jade sori ayelujara.
Iroyin sọ pe lasiko ti ọba naa nn pada si ilu rẹ, lẹyin ipade awọn lọba-lsba to lọ fun nilu Akure, ni awọn ajinigbe naa kọlu.
A gbọ pe ni agbegbe Elegbeka, ni awọn agbebọn naa ti jade lati inu igbo, ti wọn si yinbọn mọ ọkọ rẹ laimọye igba.
- Ta ni Oba Idowu Abiọdun Oniru tó wàjà nípinlẹ̀ Eko?
- Oba Folagbade Olateru-Olagbegi wàjà lẹ́ni ọdún 77
- Ìlú kò mọ ohunkóhun nípa iṣẹlẹ màálù tó kú nilu Ikarẹ- Oba Olukarẹ
- Ó ti di ẹ̀ṣẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ fún afipábánilòpọ̀ nípìnlẹ̀ Ekiti- Ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti
- Ìbálòpọ̀ ọ̀lọ́jọ́ méje mú kí ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọdún mẹ́wàá ká ní Ibadan
- Kí lo mọ̀ nípa ìbẹta kan ṣoṣo tí Alaafin Oyo bí? Wọ́n pé ọdún méjìlá báyìí
Boti lẹ jẹ pe ao ti mọ koko bi ọrọ ṣe jẹ, iroyin sọ pe awọn ajinigbe naa bẹrẹ si ni yinbọn ọkọ rẹ, lati da a duro.
Awọn miran sọ pe bi ọkọ Kabiesi ṣe n lọ, ni awọn afurasi ajinigbe naa da ọkọ duro, amọ awakọ rẹ to fura si wọn gbiyanju lati salọ. Eyi si lo mu wọn bẹrẹ si ni yinbọn mọ ọkọ naa.
Lara awọn ọta ibọn ti wọn yin lo ba Kabiesi.
Wọn gbe e de ileewosan ijọba apapọ to wa nilu Owo, nibi to ti dagbere faye.
Ijinigbe jẹ nkan to n waye ni ipinlẹ Ondo, lati bi ọdun diẹ.