Gomina Sanwo-Olu jẹ́jẹ̀ẹ́ láti fojú awakọ̀ 'container' tó pa àwọn ènìyàn mẹ́sàn-án winá òfin

Sanwo-Olu ati ijamba to waye ni Ojuelegba

Oríṣun àwòrán, LASEMA

Gómìnà ìpínlẹ̀ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti pàṣẹ pé kí wọ́n lọ fojú awakọ̀ àti ẹni tó ni ọkọ̀ container tó ṣubú pa àwọn ènìyàn ní agbègbè Ojuelegba lọ́jọ́ Àìkú ọjọ́ Kọkàndínọ́gbọ̀n, oṣù Kìíní ọdún 2023 winá òfin.

Sanwo-Olu ní ó pọn dandan láti gbé àwọn ènìyàn náà tó ti wà ní àhámọ́ ọlọ́pàá lọ sí ilé ẹjọ́ láti lọ kojú ìgbẹ́jọ́ kó le jẹ́ ìkìlọ̀ fún àwọn mìíràn.

Gómìnà Sanwo-Olu nígbà tó ń bá àwọn ènìyàn àwọn tó pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìjàm̀bá ọkọ̀ náà ní ìjọba ìpínlẹ̀ Eko kò ní fi àyè gba àwọn kọ̀lọ̀rọ̀sí ẹ̀dá kan láti máa ṣekúpa àwọn ènìyàn tó ń wá oúnjẹ òjọ́ wọn.

Àtẹ̀jáde kan tí Kọmíṣọ́nà fétò ìròyìn ìpínlẹ̀ Eko, Gbenga Omotoso fi síta ní gómìnà Sanwo-Olu ti sọ fún iléeṣẹ́ ètò ìrìnnà àti àjọ tó ń mójútó ọjà kíkówọlé ìyẹn Nigeria Ports Authority láti wá ojútùú sí bí àwọn ọkọ̀ container ṣe máa ń jábọ́.

Ó ní gbogbo òfin tó de ìrìnnà ni àwọn ọkọ̀ ńlá ní ìpínlẹ̀ Eko ni àwọn awakọ̀ gbọ́dọ̀ tẹ̀lé láti ri dájú pé àwọn òpópónà dùn-ún rìn fún àwọn awakọ̀ mìíràn.

Gómìnà Sanwo-Olu tún ṣèrántí pé lọ́dún 2022 awakọ̀ container kan Sodiq Okanlawon àti ẹni tó ni ọkọ̀ rẹ̀, Wasiu Lekan rí ẹ̀wọ̀n gbére he fẹ́sùn wí pé container rẹ̀ jábọ́ lé àwọn ènìyàn lórí tó sì pa ènìyàn mẹ́ta ní òpópónà márosẹ̀ Oshodi/Apapa ní Ilasamaja lọ́jọ́ Kẹrìndínlọ́gbọ̀n oṣù Keje ọdún 2020.

Ó sọ àrídájú rẹ̀ pé bí àwọn ṣe fi ìyà tó tọ́ jẹ àwọn wọ̀nyí náà ni àwọn máa ṣe pẹ̀lú awakọ̀ àti ẹni tó ni ọkọ̀ tó ṣekúpa àwọn ènìyàn lọ́jọ́ Àìkú.

Ó wá bá àwọn ènìyàn tó pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìjàm̀bá náà kẹ́dùn lórí ìṣẹ̀lẹ̀ láabi yìí tó sì ṣèlérí pé wọ́n máa rí ìdájọ́ òdodo gbà lórí ikú àwọn ènìyàn wọn.

'Container' ṣubú lé ọkọ̀ akérò lórí nílùú Eko, èèyàn mẹ́sàn án jáde láyé

LASEMA

Oríṣun àwòrán, LASEMA

O kere tan, eeyan mẹsan an lo ti jade laye lẹyin ti ọkọ ajagbe kan ṣubu le ọkọ akero lori lagbegbe Ojuelegba, niluu Eko.

Iroyin ni asiko ti ọkọ akero Danfo naa n ko awọn ero lọwọ ni ọkọ ajagbe kan ti ile ẹru wa lori rẹ ya bara, to si ṣubu le lori.

Ninu atẹjade kan ti akọwe agba ajọ adoola ẹmi ipinlẹ Eko, LASEMA, Olufemi Oke-Osanyintolu fi lede, o ni obinri kan lawọnj ri yọ jade laaye ninu ijamba ọhun.

Atẹjade naa ni “Nigba ti a o fi de ibi ti ijamba naa ti waye, ọkọ ajagbe kan to gbe ile ẹru ti iwọn rẹ to ẹsẹ bata ogun ti ṣubu le ọkọ akero kan lori.”

“Iwadii wa fi han pe ọkọ akero naa n ko awọn ero lọwọ ni ọkọ ajagbe naa sọ ijanu rẹ nu, to si ṣubu lẹba afara to wa nibẹ.”

LASEMA

Oríṣun àwòrán, LASEMA

“Nigba ti a gbe kọntena naa kuro lori ọkọ ọhun, ti a si ge ori ọkọ akero naa, a ri obinrin kan yọ jade laaye labẹ rẹ.”

Gẹgẹ bii ohun to sọ, wọn ti gbe obinrin naa lọ sile iwosan fun itọju pajawiri.

O tẹsiwaju pe eeyan mẹjọ lo ba ijamba ọkọ naa lọ, ti mẹta ninu wọn jẹ obinrin, mẹta mii jẹ ọkunrin, nigba ti awọn to ku jẹ ọmọde.

O pari ọrọ rẹ pe awọn oṣiṣẹ ajọ naa ṣi wa ni ikalẹ lati palẹ ijamba ọhun mọ.

Yatọ si LASEMA awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ panapana ati ọlọpaa naa wa nibẹ lati doola awọn ti ọrọ kan.