Libya Returnee: Ọpẹ́lọpẹ́ orúkọ Ooni Ile Ife ló kó mi yọ ní Libya lẹ́yìn ti mo lóyún ní óko aṣẹ́wó ti wọ́n tá mi sí

Àkọlé fídíò, Fatimah Abode Lybia

Ariwo pe ki awọn ọdọ Naijiria ṣọra fun ẹtan awọn to n ko wọn rin irinajo lọ si ilẹ okeere lọ ṣe iṣẹ aṣẹwo ni BBC Yoruba n pa lasiko yii.

Ọpọ awọn ọdọ obinrin ni wọn n jade sita bayii lati sọ ohun ti oju wón ri ni ilẹ okeere paapaa ni Libya.

Wọn n tan wọn ni ki wọn to so awọn ọdọbinrin yii di aṣẹwo nilẹ okeere.

Fatimah, ọkan lara awọn ti iya jẹ ni Libya lo tun jade sọrọ loni lori bi o ṣe fi ọsẹ mẹta rin ninu aṣale de Libya ki Azeez to ta a fun Michael to tun Fatimah ta si oko asewo nibẹ.

O ni: Nitootọ ni Azeez maan ko awọn eeyan lọ silẹ okeere ṣugbọn mi o mọ pe aṣẹwo lo nko wọn lo ṣe ni Libya.

Fatimah sọ nipa bi ọmọkunrin ara Ghana kan se yọ oun loko aṣewo ati bi wọn ṣe pada wa fọ koropọn ọkunrin naa.

O ni wọn pa ọkunrin naa nitori pe o pada ra oun kuro ni oko ẹru.

O ni niṣe ni wọn lu omo Ghana i oun loyun fun lẹyin ti o ra oun kuro nile aṣẹwo naa pa pẹlu omije.

Fatimah ni pe orukọ Oba Adeyeye Ogunwusi ti oun da ni 'embassy' ni oun fi moribọ pada wa si Naijiria pẹlu ẹmi oun.

Obinrin kan

Oríṣun àwòrán, Others

Bakan naa ni Fatimah gba awọn ọdọbinrin Naijiria ni imọran pe ki wọn ṣọra fun ẹtan pe a n lọ sile oyinbo to gbode kan yii nitori pe Canada ni oun fẹ lọ ki oun to di ero Libya