Uniabuja Abduction: : Àrá àdúgbò ní aago kan òru ní agbébọn ya wọ fásitì Abuja lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun, wọ́n jí olùka àti akẹ́kọ̀ọ́ lọ

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn agbebọn ti kọlu ilegbe awọn oṣiṣẹ fasiti ìlú Abuja, ti wọn si gbe eeyan mẹfa lọ, ni owurọ kutu ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kejì, oṣu Kọkanla.
Awọn ara adugbo sọ pe ni nkan bi aago kan oru ni awọn agbebọn naa wọ inu ọgbà naa, ti wọn si ṣíṣẹ fun bi wakati kan.
Olukọ kan sọ fun BBC pe olukọ mẹta ati ọmọ wọn meji, to fi mọ oṣiṣẹ fasiti naa kan, ni wọn ji gbe lọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Omi inú ọ̀rá ní mo lọ rà, tí orí ṣe yọ mí níbi ilé tó dà wó - Ọlọ́pàá
- Wòlíì kan fún òṣèré tíátà ní miliọnu mẹ́fà náírà láti fi tọ́jú àìsàn rẹ̀
- Ẹnikẹ́ni tó bá fẹ dóju ìbò Anambra bolẹ̀ kan ìjàngbọ̀n - Ààrẹ Buhari
- Ẹgbẹ́ TAMPAN ló mú kí ìjọba gbógun ti orísùn ọrọ̀ ajé mi - Yomi Fabiyi figbe ta
- EFCC gbé bàbá olówó Obi Cubana
- Fulani darandaran kò ṣe lè ní Kwara, wọ́n pọ̀ ju ọmọ onílùú lọ
- Bá wo ní ilé alájà 21 ṣe wó ní Ikòyí? Ẹ ṣèwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ní kíákíá - Sanwo-Olu yarí
- Èèyàn tó há sí abẹ́ ilé tó wó kò sí ẹni tó lè sọ ṣùgbọ́n òkú mẹ́rin là ri-Ọlópàá
- Ẹ bá mi bẹ ọkọ mi Aláàfin kó gbà mí padà, mo ti ṣe àṣìṣe - Olorì Damilola
- Ìyà tó ń jẹ Ife lórí òpópónà tó bàjẹ́ kò tọ́, Buhari, Oyetola, ẹ wá nǹkan ṣe sí - Ooni
Kọmisana ọlọpaa nilu Abuja, Babaji Sunday fi idi iṣẹlẹ naa mulẹ ninu atẹjade to fi sita.
O ni awọn ọdaran naa kọlu ibi ti awọn oṣiṣẹ UNIABUJA n gbe ni agbegbe Giri, ni ijọba ibilẹ Gwagwalada nilu Abuja, ti wọn si ji eeyan mẹfa gbe lọ.
Ọgbẹni Sunday sọ pe awọn agbebọn naa salọ ni kete ti wọn gburo àwọn oṣiṣẹ eleto aabo to jẹ apapọ àwọn ọmọ ologun ati ọlọpaa to lọ sibẹ lati daabo bo àwọn araalu.
Bakan naa lo sọ pe awọn oṣiṣẹ alaabo ti n sisẹ pẹlu ara ilu, lati le doola awọn eeyan ti wọn ko lọ.
Ẹ̀wẹ̀, agbenusọ fasiti naa, Habib Yakoob sọ pe awọn ko ti le fidi orúkọ awọn ti wọn ji gbe mulẹ.













