Ani Chukwuemeka: Mo ṣe fídíò láti tọrọ owó tórí àìsàn ìtọ̀ ṣúgà tó fa egbo tí kò jinná ní ìdí mi

Oríṣun àwòrán, Screen Shot
Oṣere tiata kan, Ani Chukwuemeka ti ri ẹ̀bùn miliọnu mẹfa Naira gba lati fi ṣe itọju ara rẹ.
O ti to asiko diẹ ti oserekunrin naa ti wa ni idubulẹ aisan, ko to o di pe Woli Jeremiah Fufeyin, fun ni owo naa ni ọjọ Aiku to kọja.
Fido kan ti wolii naa gbe soju opo Facebook rẹ lo se afihan igbesẹ naa, to si tun fun aya Ani ati ẹni to sin wa wa ni ẹgbẹrun lọna ẹẹdẹgbẹta naira ẹnikọkan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Omi inú ọ̀rá ní mo lọ rà, tí orí ṣe yọ mí níbi ilé tó dà wó - Ọlọ́pàá
- Ẹnikẹ́ni tó bá fẹ dóju ìbò Anambra bolẹ̀ kan ìjàngbọ̀n - Ààrẹ Buhari
- Ẹgbẹ́ TAMPAN ló mú kí ìjọba gbógun ti orísùn ọrọ̀ ajé mi - Yomi Fabiyi figbe ta
- EFCC gbé bàbá olówó Obi Cubana
- Fulani darandaran kò ṣe lè ní Kwara, wọ́n pọ̀ ju ọmọ onílùú lọ
- Bá wo ní ilé alájà 21 ṣe wó ní Ikòyí? Ẹ ṣèwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ní kíákíá - Sanwo-Olu yarí
- Èèyàn tó há sí abẹ́ ilé tó wó kò sí ẹni tó lè sọ ṣùgbọ́n òkú mẹ́rin là ri-Ọlópàá
- Ẹ bá mi bẹ ọkọ mi Aláàfin kó gbà mí padà, mo ti ṣe àṣìṣe - Olorì Damilola
- Ìyà tó ń jẹ Ife lórí òpópónà tó bàjẹ́ kò tọ́, Buhari, Oyetola, ẹ wá nǹkan ṣe sí - Ooni
Chukwuemeka, nigba to n fi idunnu rẹ han lori ẹ̀bùn owo naa sọ pe iyalẹnu lo jẹ fun oun.
O ṣalaye pe lọdun 2020 ni eto ilera oun dẹnu kọlẹ, ti wọn si ṣe iṣẹ abẹ lori egbò kan to wa ni ìdí oun nilu Owerri.
Sugbọn, nkan túbọ̀ n buru si ni, nitori pe aisan itọ ṣuga to n ṣe e, se akoba pupọ fun iwosan egbo naa.
Eyi si lo mu ko ṣe fidio kan to fi si ori ayelujara lati tọrọ owo lọwọ awọn eniyan.
Ninu fidio naa, Chukwuemeka sọ pe oju oun ti fẹ ẹ fọ́ nitori kokoro 'cataract' to ti wọ inu oju kan.
Bakan naa lo ni awọn aisan to n ṣe oun ti mu ki oun ni aisan rọpa-rọsẹ, stroke.
O wa dupẹ lọwọ wolii naa fun oju aanu to si wo ati ọwọ ọrẹ to na si ọhun.
Fidio naa ni Woli Fufeyin ri, to si pe oṣere naa si ile ijọsin rẹ lati fun lowo fun itọju ara rẹ.
Igba akọkọ kọ niyi ti Woli naa fun oṣere to n ṣàìsàn ni owo.

Oríṣun àwòrán, AFP


















