Yoruba Nation: Abdulsalam Abubakar sọ ìdí tí kò fi ṣeéṣe láti pín Nàíjíríà sí wẹ́wẹ́

Asaaju ijọba ologun tẹlẹ, Ajagunfẹyinti Abubakar Abdulsalam ti sisọ loju rẹ pe ofo ọjọ keji ọja ni aayan awọn eeyan to fẹ ya kuro lara Naijiria.
Abubakar sisọ loju ọrọ yii nibi eto ifọrọjomitoro ọrọ kan ti wọn fi sọri Ibrahim Babangida ati ogun to fi silẹ, eyi waye ni Ọjọbọ.
Abubakar lasiko to n sọ ero tiẹ lori bawọn eeyan kan se n beere fun idasilẹ orilẹede Yoruba ati Biafra kuro lara Naijiria, wa salaye idi ti erongba naa ko fi le jọ laelae.
- Àwọn ọ̀dọ́ Yoruba Nation tún ya bo Idi Iroko láti ṣí ẹnu bodè sílẹ̀, àmọ́...
- Tó bá dá Gani Adams lójú, kó dárúkọ àwọn ọ̀dàlẹ̀ inú Yoruba Nation - OPC New Era
- Mọ̀ si nípa agbẹjọ́rò Yoruba Nation tó gbé Buhari lọ sílé ẹjọ́ àgbáyé ICC
- Ẹ̀rú Fulani ni Aregbesola, ara sì ló ń ta á torí àṣeyọrí ìjìjàgbara Yoruba nation - Ilana Omo Oodua
- Òǹyẹ̀ kò lè yẹ ìwọ́de Yoruba Nation l‘Eko, mò ń bọ̀ níbẹ̀ - Sunday Igboho
- Ẹ wo àwọ́n lọ́balọ́ba tó ti ṣàtìlẹ́yìn jíjá fún Oduduwa Nation ní ilẹ̀ Yorùbá
O ni egungun ti wọnu ẹran, ẹran naa si ti wọnu egungun, ti ọpọ Yoruba si ti ba Hausa se igbeyawo, bẹẹ naa ni Fulani ti ba ẹya Igbo da ana laimọ iye igba, eyi ti yoo mu ko nira lati yapa.
"Tẹ ba ti tiẹ fọ Naijiria si yẹlẹyẹlẹ bayii, ki lẹ fẹ se nitori ko si abule tabi ilu tẹ de, tẹ ni ba ẹya Hausa, Igbo, Itsekiri tabi Yoruba nibẹ.
Tẹ ba wa da duro, nibo lẹ fẹ fi ti igbeyawo laarin ẹya kan ekeji si, nitori naa yoo nira lati fọ orilẹede Naijiria si wẹwẹ.
Amọ gbogbo wa lo yẹ ka pawọpọ lati wa ojutu si iwa aidaa tawọn kan n hu, yoo si dara kawọn eeyan maa tete tu asiri awọn onisẹ ibi, ti ko jẹ ki eto aabo wa duro re."
Adari Naijiria tẹlẹ naa wa rọ awọn araalu lati gba alaafia laaye, ki wsn si fara mọ oniruuru ẹya ati ede to wa nilẹ yii, ki wọn si tun maa wa irẹpọ laarin ara wọn.

Ọwọ tẹ Mohammed, afurasí fúlàní darandaran tó gbé ìbọn AK47 nípìnlẹ Ogun- Iléeṣẹ ọlọpàá

Oríṣun àwòrán, Nigeria police Ogun state
Owo te Mohammed, afurasi darandaran kan to gbe ibon AK47 nipinle Ogun
Ileese olopaa nipinle Ogyun ti so okunrin kan to pe oruko ara re ni Mohammed si gbaga olopaa.
Won mu u lojo Isegun, ojo kewaa, osu kejo, odun 2021 ni ipinle Ogun ni guusu iwo oorun Naijiria.
- Ọba alayé kan àti gómìnà kọ ẹnu ìfẹ́ sí mi, kí n tó fẹ́ Mr Lawal - Lizzy Anjorin
- Èèyàn 24 nínú ẹbí kan tó lo ajílẹ̀ dípò iyọ̀ jáde láyé - kọmísọ́nà ìlera
- PDP ni yóò mú ọmọ Nàíjíríà kúrò lóko ìyà tí wọn wà ní 2023 - Kola Ologbondiyan
- Goriola Hassan, má pe ara rẹ ní ọba Imobi-Ijebu mọ́, bí bẹ́ẹ̀kọ́... - Ilé aṣòfin Ogun
- Gómìnà ìpínlẹ̀ New York ní America kọ̀wé fipò sílẹ̀!
Ileese olopaa ni won gba ifitonileti nipase DPO to wa ni ekun Imeko pe awon Fulani meji kan n tin kiri agbegbe CAC Igbo Oba ni Iwoye Ketu pelu ibon AK 47 lowo won.
Ni kete ti ifitonileti yii de ódó DPO naa lo ti da awọn ọlọpaa mii sita pẹlu awọn ọdẹ aṣogbo ati awọn fijilante.
Lẹyin ọpọlọpọ wakati ti wọn ti n ṣo igbo Oba ni ọwọ tẹ awọn Fulani afurasi meji naa.
Bi wọn si ti kọkọ mu Muhammed pẹlu ibọn AK 47 to gbe dani nibi to farapamọ si naa ni wọn ti fọwọ ofin mu u.
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun ni o jẹ afurasi lara awọn ajinigbe to n ṣọṣẹ ni agbegbe Ketu.
Ninu atẹjade ti DSP Abimbola Oyeyemi to jẹ agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun fọwọ si ni o ti ni pe Komiṣọnna ọlọpaa nipinlẹ Ogun ti paṣẹ lori ọrọ naa.
Abimbola ni Komiṣọnna Edward Awolowo Ajogun ti ni ki awọn otẹlẹmuyẹ agbofimro bẹrẹ iwadii ni kia.
O tun ni ki wọn tubọ wa igbo Oba naa lọ ki wọn le mu awọn to ku to jẹ oniṣẹ ibi nibẹ.



















