Borno Dr Isa Akinbode: Gómìnà Zulum ti Borno fún Dókítà Akinbode ní àmì ẹ̀yẹ fún ìṣẹ́ takuntakun ní iléèwòsàn ìjọba

Oríṣun àwòrán, Borno State Government
Gomina ipinlẹ Borno, Ọjọgbọn Babagana Umara Zulum ti fi ọkọ tuntun ati iye owo to le ni miliọnu mẹtala da dokita Isa Akinbode lọla.
Gomina Zulum dupẹ lọwọ rẹ fun iṣẹ takuntakun to ṣe nigba to wa ni ẹnu iṣẹ ijọba gẹgẹ bi dokita.
O ni ọpọlọpọ awọn eniyan lo sa kuro ni agbegbe Mongono lasiko ikọlu ikọ Boko Haram si agbegbe naa, amọ dokita naa duro digbidigbi.
- Ìjọba Nàìjíríà tó yé kó pèsè aàbò ló kùnà lẹ́nú ojúṣe wọn- Mr Macaroni lẹ́yìn tó ti àtìmọ́lé dé
- Ṣé lóòtọ́ ni iléẹjọ́ pàṣẹ àyẹ̀wò DNA fún ọmọ Ronke Odusanya Ìdídowó, nítorí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ti ń fọnmú?
- Mọ̀ síi nípa àwọn ohun tó lè mú kí èèyàn tètè ní irun funfun lórí láì tíì di arúgbó
- Wo àwọn ọ̀rọ̀, ewì, àwòrán tí kìí ṣe 'lórí irọ́' tí o lè fi yẹ́ olólùfẹ́ rẹ sí fún Valentine
Dokita Isa Akinbode si pẹlu awọn eniyan ti ikọ Boko Haram ji gbe, amọ ti wọn fi silẹ.
Ọdun mejilelogun ni Dokita Akinbode fi ṣiṣẹ ni ileewosan gbogboogbo ti Mongono, nipinlẹ Borno.

Oríṣun àwòrán, Borno state Government
Gomina ipinlẹ Borno ni o ṣe pataki ki awọn da dokita naa lọl nitori o sin araalu ati orilẹede rẹ pẹlu gbogbo ipa rẹ.
Bakan naa ni wọn fun ọmọbinrin Dokita Akinbode ni iṣẹ lẹṣẹkẹsẹ, ti wọn si tun ṣeleri lati san owo oṣu fun dokita naa fun gbogbo ọdun to fi ṣiṣẹ ijọba pẹlu ajẹmọnu rẹ.
- Wo ǹkan márùn ún tí ọ̀pọ̀ èèyàn kò fẹ́ ní 'Valentine' 2021
- Ìjà tó wáyé ní Sasa ní Ibadan kìí ṣe ti ẹlẹ́yàmẹ̀yà- Agbẹnusọ ọlọ́pàá
- Ààrùn COVID-19 gba ẹ̀mí èèyàn 13 ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Sátidé
- Mọ̀ sií i nípa Oba Yesufu Asanike , Olubadan tí kìí fi ọ̀rọ̀ sí abẹ́ ahọ́n sọ kódà níwájú sọ́jà
- Ta ló ní kí Adebimpe Oyebade bóra nígbà tí ó darapọ̀ mọ́ Nollywood?
Gomina ọhun rọ awọn ọmọ Dokita Akinbode lati tọju baba wọn nitori alaanu eniyan lojẹ ni gbogbo ọjọ to fi ṣiṣẹ.

Oríṣun àwòrán, Borno State Government
Dokita Akinbode lo wa lati ipinlẹ Ogun, amọ o lọ si fasiti ipinlẹ Maiduguri to si durọ si ipinlẹ ọhun lati igba naa titi ti o fi fẹyinti lẹyin ọdun mejilelogun.

Oríṣun àwòrán, Borno State Government
Ikọ Boko Haram ti wa nipinlẹ Borno lati bi ọdun mẹwaa ṣẹyin, ti wọn si ti fi ọpọlọpọ ẹmi ṣofo lati igba ti wọn ti n ṣe ikọlu si agbegbe naa.
- Ìdí tí wọn kii fi jẹ́ kí obìnrin jẹ Ọ̀ọ̀ni ni Ile Ife
- Ìjọba Nàìjíríà tó yé kó pèsè aàbò ló kùnà lẹ́nú ojúṣe wọn- Mr Macaroni lẹ́yìn tó ti àtìmọ́lé dé
- Àwòràn àti bí ètò ìsìnkú Olóògbe Olóyè Lateef Jakande ṣe lọ
- Ìjà tó wáyé ní Sasa ní Ibadan kìí ṣe ti ẹlẹ́yàmẹ̀yà- Agbẹnusọ ọlọ́pàá
- Tó bá jẹ́ pé à ń gbé AK47, ìgbà táwọn àgbẹ̀ dáná sun ilé wa, ṣé aò ti ní pa wọ́n dànù? -Ọmọ Seriki Fulani













