Covid 19 Palliative: Mínísítà dèrò àgọ́ ọlọ́pàá nítorí ẹ̀sùn kíkó owó ìrànwọ́ Covid-19 sápò

Oríṣun àwòrán, NCDC/Twitter
Mínísítà dèrò àtìmọ́lé lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀sùn kàn án pé ó lu owó ìrànwọ́ Covid-19 ní pónpó.
Minisita kan ti dero atimọle ni Indonesia lẹyin ti wọn fẹsun kan pe o gbọna ẹburu ji owo iranwọ Covid-19.
Wọn ti fi panpẹ ofin mu minisita to n ri si ọrọ awujọ ni Indonesia lẹyin ti wọn fẹsun kan pe o gba riba $1.2 miliọnu lori owo iranwọ ounjẹ fun awọn ti Covid-19 ṣakoba fun.
Wọn fẹsun kan Juliari Batubara lẹtin ti awọn ọlọpaa ṣawari orisiriṣi apo ti owo ọhun wa ni ikawọ rẹ.
- Coronavirus: ''Ìjọba kò tíì pàṣẹ ìlànà ìtakété-síra-ẹni padà nínú BRT la ò ṣe máa tẹ̀le''
- Ìjọba gbé ilé ijó oníhòhò tì pa lórí ẹ̀sùn títàpá sí ìlànà àti dẹ́kun coronavirus
- Ogun abẹ́lé tó ń ja Akeredolu l'Ondo, òní la ó mọ̀ bóyá yó borí rẹ̀
- Ìyàwó mi fi mí sílẹ̀ kó lọ sílé ọkùnrin míì nínú báráàkì kan náà, àmọ́ mò sí tún fẹ́ràn rẹ̀- Sọ́jà

Oríṣun àwòrán, others
Lẹyin naa lo lọ fa ara rẹ le ọlọpaa lọwọ, eyii to mu ko jẹ ẹni keji ti aje iwa ibaje yoo ṣi mọ lori ninu ijọba Aarẹ Joko Widodo laarin ọsẹ diẹ sira wọn.
Nigba to n sọrọ lori ẹsun ti wọn fi kan minisita naa, Aarẹ Widodo sọ pe oun ko ni bo aṣiri ẹnikẹni ti wọn ba ka iwa ibajẹ mọ lọwọ.
Ṣaaju ni eto ọrọ aje Indonesia ti dẹnu kọlẹ nitori ajakalẹ arun Covid-19 to n ba gbogbo agbeye finra.
Lara ẹsun ti wọn fi kan Batubara ni pe o gba owo to le ni miliọnu kan dollar lọwọ awọn agbaṣẹṣe meji ti ijọba gbeṣẹ fun lati pese ounjẹ fun awọn ti arun Covid-19 ṣakoba fun eto ọrọ aje wọn.
- Ààrẹ àná, Goodluck Jonathan ló fún mi ní 'oògùn' tí mo fi yọ Sanusi nípò Emir Kano- Ganduje
- Èèmọ̀! Bíṣọ́ọ̀bù ń lá ata ìyàwó àlùfáà abẹ́ rẹ̀ l'Ekiti
- Ṣé lóòtọ́ ni pé Aisha Buhari ti kó lọ sí Dubai? Ẹ wo òtítọ́ ọ̀rọ̀ nàá
- Wo ìjìyà tó wà fún àwọn ọmọ Naijiria tí kò bá fi nọ́mbà NIN kún ìforúkọsílẹ̀ Siimu wọn láàrin ọ̀sẹ̀ méjì
Wọn ni minisita naa n gba nnkan bii ẹgbẹrun mẹwaa owo orilẹ-ede ọhun lori ounjẹ ti eeyan kọkan n gba lati ọdọ ijọba.
To ba jẹbi ẹsun ti wọn kan, o ṣeeṣe ko lọ sọgba ẹwọn fun nnkan bii ogun ọdun tabi ko san biliọnu kan owo orilẹ-ede ọhun gẹgẹ bii owo itanran.
- Ẹ̀yà kòkòrò Covid-19 míràn jáde ní ọgọ́ta agbègbè nílẹ̀ Gẹẹsi, àjọ eletò ìlera ni k'ára ìlú má fòyà
- Wọ́n ní kí ọ̀gá àgbà "Ede Poly" lọ rọ́kún nílé lórí ẹ̀sùn pé ó kan bẹ́ẹ̀dì sí ọ́fíìsì
- Ṣé lóòtọ́ ni Adajọ́ Àgbà Naijiria, Tanko Muhammad ti ní Covid-19?
- Ààrẹ àná, Goodluck Jonathan ló fún mi ní 'oògùn' tí mo fi yọ Sanusi nípò Emir Kano- Ganduje














