Ebonyi rape: Èèmọ̀! Àwọn adigunjalè yabo ṣọ́ọ̀ṣì, fipá bá obìnrin kan lòpọ̀, yìnbọn fún òmííràn

Aworan awọn oluwode to n pe fun ijiyia to tọ fawọn afipabilopọ

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Awọn adigunjale yabo ṣọọṣi Assemblies of God Church niluu Abakaliki, ipinlẹ Ebonyi nibi ti wọn ti fipa ba ọmọbinrin lopọ.

Iroyin ti a gbọ ni pe ẹgbẹ oṣere awọn ọdọ lo n ṣe igbaradi fun ere ori itage ti wọn fẹ ṣe lọwọ ninu ṣọọṣi tawọn adigunjale ọhun fi de saarin aago kan si meji oru.

Awọn to mọ nipa iṣẹlẹ naa sọ fawọn akọroyin pe awọn janduku naa yinbọn fun ọdọbinrin keji ni itan rẹ lẹyin to kọ ki wọn fi ipa ba oun lopọ.

Bakan naa ni a gbọ pe awọn ole naa tun ko ọpọ nkan ṣọọṣi naa lọ.

Nigba ti akọroyin iwe iroyin abẹle ṣabẹwo si ṣọọṣi ọhun, ọkan lara awọn alagba ijọ naa to ba nibẹ fidi iṣẹlẹ naa mulẹ pe otitọ lo ṣẹlẹ.

Alagba naa ṣalaye pe awọn ti fi ọrọ naa to ileeṣẹ ọlọpaa leti, bakan naa lawọn si ti gbe awọn ọmọbinrin mejeeji lọ si ile iwosan fun itọju.

Alufaa ijọ naa ko si nile nigba ti akọroyin ṣabọwo si ṣọọṣi ọhun.

Àkọlé fídíò, SS3 ní mo wà báyìí, mo sì ti gba àmì ẹ̀yẹ̀ púpò nílé-lóko gẹ́gẹ́ bí onílù - Ayansike