2019 elections: Ganduje ní òun yóò gba èsì yóòwù tó bá jáde ní ìdìbò gómìnà Kano

Ganduje

Oríṣun àwòrán, kabiru gaya

Àkọlé àwòrán, Gandije ni oun gba pe Ọlọrun mọ̀ sí èsì yóówù tó bá jáde nínú ìdìbò náà.

Gomina ipinlẹ kano, Abdullahi Ganduje ti ṣalaye ohun ti yoo ṣe bi okete ba padi ọrẹ da fun ninu idibo gomina ọjọ satide.

Ganduje ni ko si meni meji fun oun bi oun ba fidirẹmi ninu idibo naa ju pe ki oun ki ẹni to ba bori ku oriire.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Àkọlé fídíò, Ìbádọ́gba nínú ìsèlú àti iṣẹ́ láwùjọ ṣe pàtàkì fún ìdàgbàsóké

Gomina Ganduje sọ eyi di mimọ lasiko ti o fi n tọwọ bọwe adehun alaafia ni ilu Kano.

Gomina ipinlẹ Kano ọhun ni oun to ye oun ni pe Ọlọrun nii fi ọba jẹ oun naa si nii rọ ọba loye.

Àkọlé fídíò, BBC Yorùbá: Àwọn akọ̀ròyìn wa ti lọ káàkiri láti jábọ̀ ìròyìn ìbò

O ni: "Bẹẹni, mo ṣetan lati gba bi esi idibo naa ba ti ṣe lọ si gẹgẹ bii ifẹ Ọlọrun, mo si ni igbagbọ to jinlẹ ninu ifẹ Ọlọrun."

Àkọlé fídíò, Nigeria Election 2019: Ará Eko pariwo ohun márùn-ún tí wọn ń fẹ́ lọ́wọ́ ìjọba tó ń bọ̀