Osun election tribunal: PDP ti fèsì sí ẹ̀bẹ̀ ẹsùn ẹjọ́ tí Gómìnà Gboyega Oyetọla pè lórí èsì ìdìbò gómìnà Osun

Oríṣun àwòrán, Others
PDP dahun si ẹsun Oyetọla ati APC, O ni pe ki ile ẹjọ da ẹjọ naa nu.
Ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party ti sọ pe ko si ootọ ninu ọrọ awọn agbẹjọro gomina Oyetoal ti APC ni Osun.
Gomina Oyetola to jẹ oludije fun ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress (APC) ati ẹgbẹ rẹ APC lo tako esi idibo gomina to waye ni oṣu Keje, ọjọ kerindinlogun, ọdún 2022 niwaju ile-ẹjọ.
Gomina Oyetọla ati ẹgbẹ APC sọ pe awon ibo ti won di ni àwọn ijọba ibilẹ kan ju ohun ti o yẹ lọ ni ipinlẹ naa ninu eto ibo gomina to kọja.
- Ẹ ṣọ́ra fáwọn ajínigbé tí wọ́n n díbọ́n bíi ọlọ́kadà àti awakọ̀ Kórópé nipìnlẹ̀ Osun
- Ṣé lóòtọ́ ni àwọn agbébọn ṣekúpa èèkàn ẹgbẹ̀ òṣèlú APC l’Osun-
- Eèyàn márùn ún ti wà ní gbaga ọlọ́pàá ṣùgbọ́n ìwádìí ṣì ń lọ lọ́wọ́- ọlọ́pàá sọ̀rọ̀ lórí ìkọlù sọ́kọ̀ aya Gomina Oyetola
- PDP Osun ti dá a padà fún APC lórí ìgbẹ́jọ́ 'Tribunal'
- Ìpalẹ̀mọ́ Aṣékágbá ọdún Sango lágbàńlá ayé ti bẹ̀rẹ̀ nílù Oyo báyìí
- Ẹ sọ fún Ademọla Adeleke kó yé sáré kìtìkìtì, sáré kàtàkàtà mọ́, kó gbára dúró gba ìwé ìpẹ̀jọ́ mi – Oyetola
Kini o wa ṣẹlẹ bayii?
Alaga igbimọ alabojuto PDP l'Osun Dokita Adekunle Akindele ninu esi rẹ ro ile-ẹjọ Idibo lati fagile ẹbẹ Oyetola ati ẹgbẹ oṣelu APC, ti o sì ṣapejuwe rẹ pe ko ja si nkankan nitori pe isọ ni, ati pe ko si ipilẹ ti o fi le duro nitori pe fifi akoko sofo lasan ni yoo jasi.
Adekunle wa salaye siwaju pe Seneto Ademola Adeleke lo ye ki won kede gege bi ẹni tó jáwé olubori bi o ti yẹ.
O si so wi pe ko si ibi ti ibo ti ju ohun ti o yẹ kí wọn kéde lọ ni gbogbo awon ibudo idibo ti gomina Oyetola ati ẹgbẹ APC gbe wa siwaju ilé ẹjọ.
Kini nakn mii ti Adekunle tun sọ?
Akindele Adekunle tun jẹ ko di mimo pe ètò idibo naa jẹ eyiti o lọ ni alaafia, pẹlu ootọ ati igbẹkẹle laisi eyikeyi ti o ta ko ibamu pẹlu Ofin Idibo, ọdun 2022.
PDP tun je ko di mimọ pe awọn ẹsun ati ẹbẹ ti gomina Oyetola gbe lo ile ẹjọ jẹ Iro nla ti ko le fidimule ati èrò tí kò lè wa sí imusẹ.
Akindele pari ọrọ rẹ pe ipejo awuyewuye ètò ìdìbò ti gomina Oyetọla ati ẹgbẹ rẹ APC gbe wa sí ilé ẹjọ wa fún lati fi akoko sofo ati igbiyanju ni asan.
O fi kun un pe Seneto Ademola Adeleke ti o jẹ oludije fun ẹgbẹ òṣèlú PDP ati gomina ti gbogbo eniyan ipinle Ọsun yan ni o kunju osunwon lati dije fun eto idibo naa.
Imoran wo ni PDP wa gba APC ni Osun?
Nitori naa ẹgbẹ oṣelu PDP wa gba ẹgbẹ oṣelu APC ati Oyetola lamoran pe ki won gba ijakule wọn t'owaye ninu ètò ìdìbò tokoja.
O ni pe ki won dekun ijakule egan, ki won si bere ilana lati gbe isejoba kalẹ fún Seneto Ademola Adeleke ti gbogbo ilu dìbò yàn.

Iléẹjọ́ tó ń gbọ́ awuyewuye ètò ìdìbò ti fún Gómìnà Oyetola láṣẹ láti ṣàyẹ̀wò àwọn ohun eèlò ìdìbò Osun
Ilé ẹjọ to n gbo awuyewuye eto idibo ni ipinlẹ Osun ti fún Gomina Oyetola l'ase lati ṣe ayẹwo awọn ohun eèlò ìdìbò ti wọn lo lasiko idibo to kọja.
Ilé ẹjọ to n gbo awuyewuye eto idibo ni ipinlẹ Osun ti fún Gomina Oyetola l'ase lati ṣe ayẹwo awọn ohun eèlò ìdìbò ní ajọ INEC.
Awọn agbẹjọrọ fun Gomina Gboyega Oyetola ti Agbejoro agba yomi Alliu saaju lo ṣalaye fun ile ẹjọ 'Tribunal' to n gbọ ẹjọ laarin Oyetola ati Adeleke pe wọn ko tii ri Ademola Adeleke fun ni iwe ipejọ bi o ti yẹ.
- Àwọn Dókìtà bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì ní FMC Owo, Ondo
- Ó kéré tán ènìyàn 20 kú nínú ìkọlù àwọn agbẹ́sùnmọ̀mí sí ilé ìtura
- Wọ̀n tẹ̀ èèyàn méjì pa nílé ìjọ́sìn kan nìpínlẹ̀ Eko, ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ fún Olùṣọ́ àgùtàn ní Ikotun
- Mó padánù ipò gómìnà nítorí ẹgbẹ́ òṣèlú márùn-ún parapọ̀ làti kojú APC lọ́dún 2019 ni ṣùgbọ́n....- Adelabu
- Kò dẹrùn láti ṣe fíìmù fún ìgbà àkọ́kọ́ láì sí ìyá mí níbẹ̀ - Ọmọ Iyabo Oko
- Ìyàwó wọ sòkòtò fún ayẹyẹ ìgbéyéwò rẹ̀, ní wáhálà bá bẹ́ sílẹ̀
Kini o n ṣẹlẹ lori boya wọn ri iwe ipẹjọ fun Adeleke Ademola tabi bẹẹkọ?
Leyin ti awọn agbẹjọro Gomina Oyetola fidẹ mulẹ fun Adajo pe wọn ko ri Senato Ademola Adeleke lati fun un ni iwe naa bi o ti yẹ ni Adajo ba ni pe ki wọn lọ le iwe naa si ara fọto ipolongo ibo ti Adelekee ti wọn lẹ si ẹnu ọna ileejọ giga naa ni Oke fia ni Osogbo.
Alaga ile ẹjọ to n gbo awuyewuye nipa eto idibo gomina ni Ipinle Osun, Adajo Tertesa Aorga Kume ti pàṣẹ ki àwọn olujejo keji lo ọnà miran láti fí ìwé ipejo ranṣẹ sí gomina tuntun Ademola Adeleke.
Eyi waye nigba ti ikọ Oyetola sọ pe titi di isinyi, wọn koi tii ri Adeleke Ademola lati fun un ni iwe ipejo naa.
Adajo naa ni eyi wa lati lo lẹ mo ara patako iroyin to wa lenu ona ilé igbẹjọ idibo àti ṣíṣe ayẹwo àwọn ohun eèlò ìdìbò ni ile iṣẹ ajọ INEC.
Ile ẹjọ to n gbọ awuyewuye eto ibo gomina ni ipinle Ọṣun lo ti sọ ṣáájú pe awọn yoo joko lọjọ Aje oni.
Sugbọn kii ṣe lati bẹrẹ igbẹjọ lori awuyewuye eto ibo gomina ipinlẹ Ọṣun laarin gomina Oyetọla ati Ajọ INEC pẹlu Sẹnetọ Ademola Adeleke.

Wo ibi ti igbẹjọ ajọ to n gbọ ẹjọ eto idibo nipinle Osun de duro.
Ijoko awuyewuye eto idibo ni ipinlẹ Ọsun ni ọjọ Aje, ọjọ kejilelogun, osu kẹjọ, ọdun 2022 ti sọrọ ṣaaju ki ijoko to pada bẹrẹ nigba to ba ya.
Nibẹ ni won yoo ti gbọ igbẹjọ ipenija ti igun Oyetọla gbe tọ ile ẹjọ naa wa lori ipenija ti wọn n koju lati fun Sẹnetọ Adeleke ni iwe ipẹjọ.
Lara awọn agbejoro agbà olupejo Yomi Alliyu (SAN) lakoko ti o n jiyan tọka sí àwọn igbenija ti awọn dojukọ lati mu ìwé ipejo tọ olujejo seneto Ademola Adeleke ti o sì rọ ile ẹjọ naa lati lo ọna míràn.



















