Baba Ijesha: Látìgbà tí mo ti dé láhámọ́ ọlọ́pàá ni mo ti ń rí ẹ̀jẹ̀ nínú ìgbọ̀nsẹ̀ mi
Lẹyin ti ile ẹjọ gba oniduro rẹ lori ẹsun aṣemaṣe pẹlu majesin ti wọn fi kan an, gbajumọ oṣere tiata, Ọlanrewaju James ti ọpọ mọ si Baba Ijẹṣa, ti pariwo sita pe oun n ri ẹjẹ ninu igbọnsẹ oun.
Baba Ijẹṣa sọrọ soke ninu fidio kan to n ja ranyinranyin kaakiri lori ayelujara nibi ti wọn ti n se ayẹwo ara rẹ ni ileewosan to ti lọ gba itọju.
Ninu fidio naa ni Baba Ijesha ti salaye pe lati igba ti oun ti ti ahamọ ọlọpaa de, ilera oun ko ri bakan naa mọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Dino Melaye sọ̀rọ̀ sókè lórí ọ̀rọ̀ ìfẹ́ tí wọn ló ní pẹ̀lú àwọn òṣèrẹ tíátà
- Olórin bíi Tiwa Salvage ni mo fẹ́ jẹ́ lọ́jọ́ ìwájú, ẹ má jẹ́ kí ń kú - Chidima afurasí apààyàn
- Àwọn àjẹ́ fọhún síta lórí ìgbésẹ́ àti pín Nàìjíríà sí wẹ́wẹ́
- Ẹgbẹ́ òṣèré tíátà, TAMPAN fọnmú mọ́ Iyabo Ojo àti Nkechi Blessing lọ́wọ́
- Bí ìlànà ìsìnkú TB Joshua yóò ṣe lọ rèé - Mọ̀lẹ́bí kéde
- Yomi Fabiyi fi ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí Iyabo Ojo lẹ́yìn béèlì Baba Ijesha
- Iyabo Ojo gbé fídíò míì síta nípa Olofana àti ìhùwàsí àwọn onítíátà lẹ́yìn béèlì Baba Ijesha
- Agbébọn jí Ọba alayé lọ lọ́nà oko l‘Ekiti, Olorì móríbọ́
- Olofa Ina tọrọ àforíjìn lọ̀wọ̀ àwọn òṣèré tíátà obìrin lórí ọ̀rọ̀ tó sọ níbi ìgbẹ́jọ́ Baba Ijesha
Baba Ijesha ni wọn fi bata gba oun lori lọpọ igba ati ni bẹbẹrẹ idi lasiko ti oun wa ni ahamọ, eyi to ni o wa lara idi ti ilera oun ko fi ji pepe mọ.
Nigba to n dahun ibeere ti dokita n bii, Baba Ijesha dahun pe "Bi igba ti wọn n lu olu lori mi lo ṣe maa n ri, bi ori ba n fọ mi, ti irora rẹ si maa n kọja afarada."
Ni Ọjọbọ, ọjọ kẹrinlelogun oṣu kẹfa ọdun 2021 ni ile ẹjọ gba oniduro Baba Ijẹsha lẹyin ọpọlọpọ ọsẹ ni ahamọ ọlọpaa ni Panti nilu Eko.














