NDLEA mú dókítà àti sọ́jà lórí ẹ̀sùn títà egbòogi olóró

Oríṣun àwòrán, others
Ọwọ ajọ to n gbogun ti egboogi oloro ni Naijiria , NDLEA, ti tẹ dokita kan, Jane Chioma Ofoma, ti wọn fẹsun kan pe o n ta egboogi oloro lori ayeujara.
Wọn fẹsun kan oniṣegun oyinbo naa pe o n lo ṣọọbu rẹ lori ayelujara, Omachi's Kitchen, nibi to ti dibọn pe onjẹ ni oun n ta lati maa ta egboogi naa eyii to ti po mọ suiti ati bisikiti.
NDLEA tun fi ṣikun ofin mu ọkunrin kan to ti fi igba kan jẹ jagunjagun ri, Sgt Ibrahim Musa, lẹyin ti wọn ka nnkan bii kilo mẹtala igbo mọ lọwọ.
- Ọlọ́pàá tó tẹ George Floyed lọ́rùn pa ti rí ẹ̀wọ̀n ọdún méjìlélógún àti oṣù mẹ́fà he l'Amẹrika
- Òní ni ìwọ́de Yoruba Nation yóò wáyé ní ìpínlẹ̀ Kwara
- Ìwé ẹ̀rí àyẹ̀wò oògùn olóró yóò di dandan fún ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ gbé'yàwò láìpẹ́- Buba Marwa NDLEA
- Ọmọ ọdún méje ni mo ti ń digunjalè, ogun ìdílé ló fàá, afurasí ṣàlàyé l'Ondo
- Wo ìlànà tí ó máa tẹ̀lé láti wo èsì ìdánwò 2021 Jamb UTME rẹ lórí ayélujára àti SMS
- Gọngọ́ sọ, àwọn Ṣọ́jà lé ọlọ́pàá lùgbẹ́ lágọ́ ọlọ́pàá l' Osogbo
Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ NDLEA, Femi Babafemi fi sọwọ si awọn akọroroyin, o ni ọwọ tẹ awọn afurasi naa ni ipinlẹ Edo lẹyin iwadii awọn ọtẹlẹmuyẹ awọn.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, awọn ọtẹlẹmuyẹ naa ya bo agbegbe ti awọn afurasi ọhun wa ni No 1 Winners Way, Auchi, nibi ti wọn ti ka nnkan bii ọgọrun bisikiti ti wọn fi egboogi igbo po mọ dokita naa lọwọ.
O ni "Chioma, to jẹ ẹni ọdun mẹrindinlọgbọn kẹkọọ jade nile ẹkọṣẹ iṣegun fasiti Nsukka, o si lọ sin ni ile iwosan fasiti Benin."
Babafemi sọ pe afurasi ọhun ti jẹwọ fun awọn pe lootọ ni oun maa n po egboogi "skunk" mọ bisikiti ti oun n ta lori ayelujara.
O sọ siwaju si pe awọn mu jagunjagun tẹlẹri, Musa, ni Oke-Odo, iyẹn lagbegbe Tanke, niluu Ilorin lọjọ kẹtadinlogun, oṣu ti a wa yii.
Alukoro NDLEA naa ṣalaye pe "Sgt Musa ti fi igba kan ṣiṣẹ ni barake Abati to wa niluu Eko ri, ko to lọ ṣiṣẹ pẹlu 17 battalion niluu Chibok, nipinlẹ Bornu, lẹyin naa lo salọ kuro nidii iṣẹ Ologun lọ siluu Ilorin."
O ni Musa jẹwọ fun awọn pe asiko ti oun wa ni Chibok ni oun pade ẹni to n ko egboogi igbo "Arizona" fun oun lati maa ta."
Atẹjade naa tẹsiwaju pe NDLEA tun fi ṣikun ofin mu ọkunrinẹni ọgbọn ọdun kan, Emmanuel Ehiramhen, to n ta egboogi kokeni niluu Ekpoma, nipinlẹ Edo yii kan naa.
Nigba to n da si ọrọ naa, ọga agba ajọ NDLEA, ajagunfẹyinti Brig. Gen. Mohamed Buba Marwa sọ pe afojusun awọn ni lati ri daju pe awọn kasẹ gbogbo ohun to jọ mọ titi ati lilo egboogo oloro ni Naijiria.
- Iyabo Ojo, mẹ́nu kúrò lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha ní báyìí tí ọ̀rọ̀ ti dé iwájú mi - Adájọ́ Toyin Taiwo
- Òní ni ìwọ́de Yoruba Nation yóò wáyé ní ìpínlẹ̀ Kwara
- Ọlọ́pàá tó tẹ George Floyed lọ́rùn pa ti rí ẹ̀wọ̀n ọdún méjìlélógún àti oṣù mẹ́fà he l'Amẹrika
- Mó ṣèlérí láti buwọ́lu àtúntò Naijiria, Ilé Aṣòfin o kù sí ọwọ́ yín - Ààrẹ́ Buhari
- Èèyàn kan ti kú, 99 di àwátì lẹ́yìn tí ilé alájà méjìlá wó lulẹ̀ l'óru
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń ṣelédè lẹ́yìn Ajimobi, èrò wọn ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀!
















