Ṣáájú ni obìrin náà ti kọ́kọ́ di àwátì ní nǹkan bíi ọ̀sẹ̀ méjì sẹ́yìn kí àṣírí tó tú

Oríṣun àwòrán, others
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Delta ti wu oku obinrin ẹni ọdun mẹrindilogoji kan ti wọn sọ pe alabagbe ati ẹsọ ẹnu ọna rẹ ṣekupa ni ilu Asaba.
Obinrin ọhun ti orukọ rẹ n jẹ Obiagelu Onakanse ni wọn sin sinu ile kan lagbegbe GRA ni ilu naa.
Ṣaaju ni obinrin ọhun ti kọkọ di awati ni nnkan bi ọsẹ meji ṣeyin ki asiri to tu pe awọn to sun mọ ọ lo dẹmi rẹ legbodo.
Iroyin ni apa ibi to ti farapa wa lori rẹ, bakan naa ni oju ibi ti wọn ṣa a ladaa ṣi wa lara rẹ lẹyin ti wọn wu oku rẹ tan.
Nigba to n ba awọn akọroyin sọrọ lori iṣẹlẹ ọhun, igbakeji kọmiṣona ọlọpaa ipinlẹ Delta, Faleye Olayele gboṣuba kare fun awọn agbofinro fun iṣẹ takuntakun ti wọn lori iṣẹlẹ naa.

Oríṣun àwòrán, others
O fi kun pe ileeṣẹ ọlọpaa yoo tuṣu de isalẹ ikoko gbogbo bi ọrọ naa ṣe ṣẹ.
- Ẹ fura o, Boko Haram ti pàgọ́ sí Abuja, yóò ṣe ìkọlù láìpẹ́ - Iléèṣẹ́ Aṣọ́bodè lọgun
- Ká ní ọmọ Buhari fẹ́ mi, màálù 150 ní màá fi dána - Olólùfẹ́ míì tó tún yọjú
- Tinubu, yé é sọ̀rọ̀ abẹ́lẹ̀, bọ́ sí gbangba láti bèèrè àtúntò Nàíjíríà lọ́dọ̀ Buhari - Afẹnifẹrẹ
- Ọjọ́ Ìṣẹ́gun yóò ro lásìkò ìwọ́de lórí èlé owó epo - Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́
Faleye ṣalaye pe afurasi ti wọn gbamu kọkọ sẹ pe oun ko mọ ohunkohun nipa iṣẹlẹ ọhun, ṣugbọn o ko ọrọ rẹ jẹ ni ọjọ kẹta, oṣu Kẹsan an, ọdun 2020.
igbakeji kọmiṣona ọlọpaa sọ siwaju si pe bi oloogbe naa ṣe dero ọrun ko ṣeyin oun.
O ni afurasi naa lo mu awọn agbofinro lọ ibi to sin oku obinran ọhun si lẹyin to gẹ ẹmi rẹ kuru.
- Risikat olójú búlù dí aya Wasiu ní ìlànà Islam, tẹbí tará péjú síbẹ̀
- Aàrẹ Marcelo Rebelo de Sousa ẹni ọdùn 71 bẹ́ sómi láti dóòlà obìnrin méjì tó fẹ́ rì sómi
- Ó ń bọ̀ lọ́nà! Odunlade Adekola, Femi Adebayo, Jenifa ṣi aṣọ lójú àwọn fíìmù tuntun tẹ́ẹ ti ń retí
- Ẹ̀rọ CCTV tú àsírí ọkùnrin ẹni ọgbọ̀n ọdún tó fi ipá bá ọmọ ọdún mọ́kànlá lòpọ̀













