Osun state election 2022: Kosun state election 2022 ní PDP ni yóò borí nínú ètò ìdìbò tó ń bọ̀

Ademola Adeleke

Oríṣun àwòrán, facebook/Southwest-Frontier

Lẹyin ọpọlọpọ awuyewuye ninu ẹgbẹ oṣelu PDP nipa yiyan ọmọ oye ni ipinlẹ Osun, awọn oludije mejeji to n du ipo gomina ni awọn ti sẹtan láti ṣe iṣẹ́ papọ.

Ademola Adeleke ati Ọmọba Dotun Babayemi ni wọn kede pé opin ti de ba irinjiyan tí o waye ninu ẹgbẹ osẹlu PDP ni Ìpinlẹ Osun lẹyin tí ẹgbẹ kan ti wọn n pe ni "Eyitayo Jegede reconciliation committee" ṣe abewo sì ipinlẹ naa .

Ninu atẹjade ti ẹgbẹto n ri si imura idibo fun Ọmọba Dotun Babayemi fi sita lọjọ Aje, wọn ni nnkan to kan awọn ni bi ẹgbẹ oselu PDP yoo ṣe bori ninu eto ìdibo gomina to n bọ ni ipinlẹ Osun.

Ẹgbẹ naa ni awọn wa fun alaafia ati ifọwọsowọpọ ẹgbẹ lati borí awọn alatako ninu eto ìdibo gomina to n bọ.

Atẹjade naa ni "A ri awọn to daa fun ẹgbẹ oselu PDP ni ipinlẹ Osun, ti a si gbagbọ pe pẹlu suuru, a oo borí àwọn alatako."

Ẹgbẹ Dotun Babayemi wa rọ awọn ọmọ ẹgbẹ oselu PDP ni Ìpinlẹ Osun lati ma dẹkun ìṣẹ ribiribi ti wọn n se lati ri pe ẹgbẹ oṣelu PDP bori ninu eto ìdibo ọhun.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold

Ki ni Ademola Adeleke sọ?

Bakan naa, Sẹnetọ Ademola Adeleke ninu ọrọ rẹ ni ipade naa ni o wa ninu imura oun lati ri pe ẹgbẹ oselu PDP ipinlẹ Osun wa ni iṣọkan ninu igbiyanju lrẹ ati borí alatako ninu eto ìdibo to ń bo.

Adeleke ni oun ti ṣetan lati fọwọsowọpọ pẹlu awọn ọmọ ẹgbẹ lati borí ninu eto ìdibo gomina to n bo.

"Bibori ẹgbẹ oselu APC jẹ nnkan pataki fun awa ọmọ ẹgbẹ PDP tori pe oun ni kọkọrọ fun wa ninu eto ìdibo apapọ ni ọdun 2023.

Ipade naa ni Eyitayo Jegede darí pẹlu awọn agba ọjẹ ninu ẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Osun.

Àkọlé fídíò, Alaafin stool: Wo ẹni tó ṣeẹṣe pé kí Aláàfin kàn lẹ́yìn ìpapòdà Oba Lamidi Adeyemi