Deborah Samuel: Gani Adams tutọ́ sókè fojú gbàá lórí ìtàjẹ̀sílẹ̀ arábìnrin Deborah ní Sokoto, ohun tó sọ rèé

Oloye Gani Adams, Aarẹ Ọna Kakanfo tuntun
Àkọlé àwòrán, Ojuse Aarẹ Ọna Kakanfo ni lati daabo bo ilẹ Yoruba lọwọ ikọlu awọn ajeji

Aarẹ Ọna Kakanfo Ilẹ Yoruba patapata Iba Gani Adams ti dasi ọrọ iṣekupani arabinrin Deborah Samuel toi waye ni ipinlẹ Sokoto.

Gani Adams sọ pe awọn to ṣeku pa arabinrin naa n gbero lati da ogun ẹlẹyamẹya ati ẹlẹsinmẹsin silẹ ni ilẹ Yoruba ni.

O fi ọrọ yi sita gba tọwọ agbẹnusọ rẹ Kehinde Aderemi lọjọ Aiku to kọja yi.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold

Ninu atẹjade naa, Iba Adams ni ''ọrọ ti doju rẹ bayi ni Naijiria ati pe ti wọn ko ba wa nkan ṣe si, o le di wahala ti ipa ko ni le ka''

O kilọ pe agbegbe awọn ti gburo pe awọn alaburu kan ti n wọle si ilẹ Yoruba pẹlu erongba ki wọn dana sun ilẹ Yoruba.

O ni awọn ko ni faaye gba ipete peero wọn nitori o ṣeeṣe ki o da wahala ẹlẹsin ati ẹlẹyamẹya silẹ laarin awọn eeyan.

''Awọn alakatakiti ẹsin yi ni ibi ti wọn fọkan si.Ireti wọn si ni pe ki wọn da wahala silẹ ni apa iwọ oorun Guusu wa, ṣugbọn a ko ni faaye gba wọn''

O bẹnu atẹ lu isọwọ bi wọn ṣe pa arabinrin Deborah Samuel ni ipakupa to si ni awọn agbofinro tete mu awọn to wa nidi iku rẹ ki wọn si foju wina ofin ni kiakia.

Aarẹ Ọna Kakanfo ilẹ Yoruba sọ pe ko pẹ yi lawọn agbarijọpọ eleto aabo ni Ilẹ Yoruba lọgun sita lori bi awọn ajoji ti kii ṣe ọmọ Naijiria ṣe yawọ ilẹ Yoruba.

Àkọlé fídíò, Mathew Okotie, Driver who returned laptop: Ṣé àwọn awakọ̀ olóòtọ́ ṣi kù ní Nàìjírípa?

O ni awọn ke gbajare nitori pupọ awọn wọnyi lo maa n gbe ọbẹ ati nkan ija oloro mii rin kaakiri ati pe wọn ṣetan lati ṣaburu fawọn eeyan.

O tẹnu mọ pe iṣẹlẹ iṣekupani Deborah yi ṣafihan aibikita awọn alakatakiti yi.

''Wọn dawọ jọ na, wọn ṣe leṣe,wọn lu debi iku wọn si dana sun lalae kaanu rẹ''Iba Adams wa parọwa si Gomina ipinlẹ Sokoto Aminu Waziri Tambuwal lati daabo bo gbogbo araalu.

Àkọlé fídíò, Ó yẹ kí a wádìí ikú tó pa Oba Lamidi Adeyemi, Baba gbọ́dọ̀ padà- Sat Guru Maharaj-ji

O ni ko ṣa gbogbo ipa rẹ lati ri pe ọwọ tẹ awọn to wa nidi iṣẹlẹ yi to fi mọ awọn alatilẹyin wọn.

''Ofin wa nilẹ yi to fidi idaabo araalu kọọkan mulẹ a si gbọdọ bọwọ fun iru ofin yi.Ẹnikẹni to ba tako ofin yi gbọdọ foju wina ofin ni''