PDP NEC 2023 decision: Àríwá Nàìjíríà ní alága PDP yóò tí wà ṣùgbọ́n lórí ọ́rọ́ 'Zoning' ipò ààrẹ...

Aworan ipade ẹgbẹ PDP

Oríṣun àwòrán, PDP

Ẹgbẹ oṣelu Peoples Democratic Party ti fẹnuko pe awọn yoo yan alaga ẹgbẹ lati ariwa orileede Naijiria.

Eleyi jẹ ọkan lara abajade ipade ti wọn ṣe nilu Abuja lỌjọbọ.

Ọrọ ibi ti wọn yoo gbe ipo alaga ẹgbẹ si jẹ eleyi ti awọn eeyan ti n sọ iriwisi ọtọọtọ le lori lẹnu ọjọ mẹta yi.

Sẹnẹtọ Ibrahim Tsauri to jẹ akọwe agba ẹgbẹ naa sọ fun BBC pe koko mẹrin pataki lawọn ipinu le lẹyin ipade naa.

Awọn ipinnu mẹrin naa ree:

  • Alaga ẹgbẹ gbọdọ wa lati apa ariwa orileede Naijiria
  • Wọn yoo ṣe paṣiparọ awọn ipo laarin awọn to wa lati Ariwa Naijiria ati awọn to wa lati Guusu Naijiria
Àkọlé fídíò, Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olodumare lè lo Aje láti gbé ẹ lọ síbi ire?- Abiodun Fatomilola
  • Pasiparọ ipo yi kokan awọn to di ipo mu lọwọlọwọ bayi
  • Gbogbo ọmọ ẹgbẹ lo lẹtọ ki wọn gbọ eyikekyi ẹhonu to ba mu wa.
Àkọlé fídíò, Samuel Oluwafemi sọ bí Covid 19 ṣe bí ìdíje oníjó àti eré fún àwọn Odi àti Adití sí rere

Ipinnu yi wa ni ibamu pẹlu aba ti igbimọ to da lori pinpin ipo ti Gomina Ifeanyiu Ugwuanyi dari rẹ da.

Kola Ologbondiyan to jẹ akọwe ipolongo ẹgbẹ sọ pe lori ọrọ ibi ti wọn yoo gbe oludije ipo aarẹ si awọn ko ti fẹnu ko tan.

PDP

Oríṣun àwòrán, @PDP

O ni gbogbo ọmọ ẹgbẹ ni yoo sọ ẹni ti yoo lanfaani lati dije dupo aarẹ.

Atiku Abubakar to jẹ ọkan lara awọn eekan ẹgbẹ ti ṣaaju sọ pe ki ẹgbẹ ma ṣe lo ilana zoning lati fi yan ẹni ti yoo dije ipo aarẹ.

Àkọlé fídíò, Adeyemi Olubunmi Crown: Láti ìgbà ti mo ti fún ọkọ mi ni ẹ̀bùn mọ́tò ni ìfẹ́ wa ti yàtọ̀

O sọ pe ọrọ ibi ti aarẹ ba ti wa ti n da wahala silẹ lati ọjọ to ti pẹ

''Ko si nkan to n jẹ aarẹ to wa lati Guusu tabi lati ariwa aarẹ kan ṣoṣo lo wa eyi si ni aarẹ Naijiria fun Naijiria fawọn ọmọ Naijiria''.

Àkọlé fídíò, Nàìjíríà kàn wà ni, ẹ ò páàsì, ẹ ò féèlì, ẹ ò kúrò ní kíláàsì kan náà - Àwọn ọ̀dọ́

Àwọn adari ẹgbẹ́ òṣèlú PDP bẹ̀rẹ̀ ìpàdé lórí ọjọ́ ọ̀la ẹgbẹ́ náà

Oni, ọjọ keje, oṣù Kẹwaa, ọdún 2021 ni ẹgbẹ oṣelu PDP n ṣe ìpàdé awọn adari rẹ èyí tí ọ le yọri sí itẹsiwaju tabi ifasẹyin ẹgbẹ náà.

Àkọlé fídíò, Adepoju Abdulsalamm ẹni ọdun 18 tó n fi kẹ̀kẹ́ dára fi kiri ẹja tó fi n tà wàràwàrà

Ireti wa pé àwọn adari ẹgbẹ ọhun yóò jíròrò lórí gbígbé ipò Ààrẹ lọ sí ẹlẹkunjẹkun eyiti ti igbimọ kan ti gomina Ifeanyi Ugwuanyi darí rẹ daba.

Lasiko to n tẹwọ gba esi ìpàdé igbimọ náà, alaga fidihẹ ẹgbẹ ọhun, Yemi Akinwonmi sọ pé ìpàdé tí yóò waye lonii ni yóò ṣàpèjúwe ọjọ iwájú ẹgbẹ oṣelu PDP.

Igbimọ náà ti kọkọ sọ ṣáájú pe kí wọn paarọ ipo awọn adari ẹgbẹ náà, ki awọn èèyàn òkè ọya paarọ ipò wọn pẹlu awọn èèyàn ìhà gúsù.

Ti awọn adari ẹgbẹ náà bá gbe aba yìí wọlé, ọ n túmọ sí pé apa oke ọya ni alaga tuntun ẹgbẹ náà yóò ti wa.

Àkọlé fídíò, Africa Eye wádii àwọn tó wà nídìí ìgbésùmọ̀mí ni Mozambique

Awọn ipò míràn yóò tún lọ sí òkè ọya, bíi ipo akápò gbogbogbò, ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Nigba ti akọwe gbogbogbo yóò wá láti ìhà gúsù, to fi mọ alukoro, atawọn ipo mii.

Àkọlé fídíò, Ẹni tó bá ni kí n fi iṣẹ́ kòkò mímọ sílẹ̀, mi ò lè fẹ́ẹ láéláé - Adekemi Àgùnbánirọ̀

Ẹwẹ, awọn èèyàn kan ninu ẹgbẹ ọhún ti n fapajanu pe imọran igbimọ náà dára, sùgbón kò ṣe é tẹle.

Wọn ni imọran naa kii se fun itẹsiwaju ẹgbẹ oṣelu PDP, bi ko ṣe fún apo awọn èèyàn kan nínú ẹgbẹ náà.