Suspected Kidnappers: Ọwọ ọlọ́pàá tẹ afurasí ajínigbé tó máa n dibọn bí dírẹ́bà láti jí àwọn arìnrìnàjò gbé

Aworan ajinigbe

Oríṣun àwòrán, Nigeria Police

Ileeṣẹ ọlọpaa lorileede Naijiria sọ pe ọwọ awọn ti tẹ awọn afurasi ajinigbe ogun to n da omi alaafia ilu ru lagbegbe iwọ oorun ariwa Naijiria.

Alukoro ọlọpaa Sunday Mba to fi ọrọ yi sita ninu atẹjade kan sọ pe awọn ti ọwọ tẹ jẹ ọmọ ikọ ajinigbe meji ọtọọtọ to n ji awọn eeyan gbe loju ọna marosẹ.

Mba sọ pe ibọn atamatase mọkanla ati ado oloro aṣekupani mọkanla lawọn ri gba lọwọ awọn afurasi yi.

Gẹgẹ bi atẹjade to fi sita ti ṣe sọ, ogunagbongbo inu awọn afurasi yi a maa dibọn bi awakọ lati le fi ji awọn eeyan to ba wọ ọkọ rẹ gbe.

Wọn ni bo ba ti gbe awọn ero tan, yoo ta awọn akẹgbẹ rẹ lolobo ti wọn yoo si da awọn eeyan naa lọna.

Bi wọn ṣe n gba owo lọwọ awọn ti wọn ji gbe, bẹẹ naa ni wọn a tun maa pa awọn mi ninu awọn to ba ko si wọn lọwọ.

Aworan awọn ajinigbe

Oríṣun àwòrán, Nigeria Police

Yatọ si awọn ajinigbe wọn yi, alukoro ọlọpaa sọ pe awọn tu mu ikọ awn to n ji ọkọ gbe ti wọn a si tun maa ṣe fayawọ ọkọ.

Ọkọ mẹẹdogun ni wọn ri gba pada lọwọ wọn ti a si gbọ pe wọn a maa gbe ọkọ ti wọn ba jigbe lọ si orileede Niger lati lọ ta a nibẹ.

Àkọlé fídíò, Samuel Oluwafemi sọ bí Covid 19 ṣe bí ìdíje oníjó àti eré fún àwọn Odi àti Adití sí rere