EFCC Board Screening: Ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin yan ẹ̀ní tó tí bẹ̀rẹ̀ ilélkọ́ kí wọ́n tó dé ilé ayé gẹ̀gẹ̀ bí ìgbìmọ̀ EFCC

Oríṣun àwòrán, OTHERS
Ile Igbimọ Aṣofin Agba ti buwọlu arakunrin Yahaya Mohammad lati ipinlẹ Yobe gẹgẹ bi ọkan lara awọn igbimọ Ajọ EFCC to n gbogun ti iwa ibajẹ ati jẹgudujẹra ni Naijiria.
Amọ, lasiko ti ile igbimọ aṣofin agba naa n ṣe ayẹwo awọn iwe ẹri rẹ ni wọn ri i pe o ti bẹrẹ ileẹ̀kọ́ ki wọn to bi i si aye nipa ọjọ ori to fi silẹ̀.
Sẹnetọ to fi aṣiṣe to wa ninu ẹri rẹ naa han ni ṣẹnatọ to n soju agbegbe iha ariwa ipinlẹ Jigawa, Hassan Hadeija.
- Èkó àti Rivers nìkan kọ, wo àwọn ìpínlẹ̀ Gúúsù-Gúúsù mi tó ṣetán láti lọ sílé ẹjọ́ gíga jùlọ lórí VAT
- À ò ni gbárùkù tì gbogbo ẹ̀yin gómìnà ìhà Gúúsù tó bá tako kíkẹ́ràn jẹ̀ - Miyetti Allah
- Nkechi Blessing sọ̀rọ̀ nípa ikú ìyá rẹ̀, ó tún tú àṣírí kàbìtì nípa ìhùwàsí ara rẹ̀ táyé kò mọ̀
- Kìí ṣe pé ìjọba ń fi ọwọ́ jẹ́jẹ́ mú àwọn jàndùkú o - Lai Mohammed
- Àṣírí ọ̀rọ̀ àti dúkìá ìkọ̀kọ̀ ẹbí aarẹ Uhuru Kenyatta tú
- Kàyééfì! Ẹ wó ìyàwó tó ṣán ọkọ rẹ̀ mọ́lẹ̀ tó sí fí àdá bẹ orí rẹ̀!
Hadeija lasiko ijoko ile ni asiko ti Muhammad lọ si ileẹ̀kọ́ saaju igba ti wọn bi nitori ọdun 1969 ni wọn bii gẹgẹ bi iwe ẹri rẹ ṣe ṣọ, to si bẹrẹ ileẹkọ alakọbẹrẹ ni ọdun 1968.
''Oun ti mo ri ninu iwe ẹri arakunrin Muhammad ni pe Muhammad ti bẹrẹ ileewe rẹ ki wọn to bii eleyii ko bojumu.
Ọjọ Kọkandinlọgbọn, Oṣu Kẹsan an, ọdun 1969 ni wọn bi amọ o bẹrẹ ileẹkọ alakọbẹrẹ Central Primary School ni ọdun 1968.
Bakan naa ni iwe ẹri rẹ fihan pe o lọ si ileewe giga meji lẹẹkan naa, eleyii ti yoo nira lati ṣe lasiko naa.

Oríṣun àwòrán, EFCC
Iwe ẹri rẹ ni o lọ si ileẹkọ Borno Teachers' College ni ọdun 1975 si ọdun 1988, to si tun lọ si ileẹkọ College of Administration ni ọdun 1980 si ọdun 1981.
Ti eleyii ba jẹ aṣiṣe afi ọwọ kọ, ki wọn tete ṣe atunṣe ki o le wa ni akọsilẹ to dara.
Amọ, Alaga igbimọ to ṣe ayẹwọ awọn ti wọn yan si igbimọ ajọ EFCC naa,Suleiman Abdu Kwari ni ki wọn yan an nitori o kunjuwọn.
- Samuel Oluwafemi sọ bí Covid 19 ṣe bí ìdíje oníjó àti eré fún àwọn Odi àti Adití sí rere
- Ọjọ́ burúkú èṣù gbomimú ní Ọyọ! igi ńlá wó pa ọ̀pọ̀ ènìyàn
- Irọ́ ni, kò sóhun tó jọ pé a fẹ́ gbẹ́sẹ̀ lé owó 'domiciliary account' àwọn ènìyàn Nàìjíríà- CBN
- Olubadan ti ilẹ̀ Ibadan rọ Báàlẹ̀ Lagelu Abọke kúrò lóyè lórí ẹ̀sùn aṣemáṣe
- Ṣé lóòótọ́ ní pé EFCC mú ìyàwó Gómìnà Ganduje ìpínlẹ̀ Kano?
Sẹnetọ Kwari ni Mohammad ko ni ẹsun iwa ibajẹ kankan ti ẹnikẹni le tọka si.
Ile Igbimọ Aṣofin ko gbiyanju lati ṣe atunṣe awọn aṣemaṣe to wa ninu iwe ẹri rẹ ki wọn to buwọlu gẹgẹ bi ọkan lara awọn igbimọ Ajo EFCC.
Muhammad wa lati ipinlẹ Yobe kan naa pẹlu aarẹ ile igbimo Asofin, Ahmad Lawan.
















