Kwara family food poiison death: Ọmọ ìyá kan náà mẹ́ta kú lẹ́yìn tí wọ́n jẹ Àmàlà ní Ilorin

Oríṣun àwòrán, @Kwara
Ọfọ̀ nla miran tun ṣẹ nijọba ibilẹ Ilorin East, nipinlẹ Kwara lọjọ Ìṣẹ́gun, lẹyin ti eeyan mẹta kú ninu ẹbi kan.
Iroyin ti a ko ti i le fidi rẹ mulẹ sọ pe majele wa ninu oúnjẹ kan ti wọn jẹ lo fa iku ojiji.
A gbọ pe ọmọ iya kan naa marun-un ni iṣẹlẹ naa ṣẹlẹ si lẹyin ti wọn jẹ amala tán.
- Àjọ̀dún odò Ẹ̀rìn, omi tí wọn kò gbọdọ̀ pa ẹja abàmì inú rẹ̀ wáyé nílùú Erinjiyan
- Ẹ wo ibi ọ̀rọ̀ dé dúró lórí àwọn afurasí tó lọ́wọ́ nínú ikú Tolulope Arotile
- Buhari fẹ́ dá Naijiria padà sí ọdún 1984, ṣùgbọ́n a kò ní gbà fun- Femi Falana
- Ọmọ Naijiria 350 ni ẹ̀mí wọn sọnù nínù ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi lọ́dún 2020
- A ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ẹ̀sùn tí Igboho, Akintoye àti Ilana Omo Oodua gbé wa síwájú wa- ICC
- Kò sọ́jà mọ́! A ti ti Ọjà Ladipo pa nítorí rògbòdìyàn tó bẹ́ sílẹ̀ níbẹ̀ - `ijọba ìpínlẹ̀ Eko
Ni kete ti wọn jẹ oúnjẹ naa tan ni wọn bẹrẹ si ni pariwo inu rirun, ti wọn si tun n bi.
Eyi to mu ki wọn o gbe wọn lọ sileewosan kan nilu Ilorin.
Awọn mẹta ni aisan kọkọ bẹrẹ lara wọn, ti wọn si gbe wọn lọ si ileewosan itọju àwọn ọmọde Children's Specialists Hospital, Ilorin.
Nibi ti wọn ti n gbiyanju lati doola ẹmi awọn mẹtẹẹta, ni wọn tun gbe awọn meji yooku lọ si ileewosan miran.
Ni ileewosan si ni wọn ti sọ fun wọn pé àwọn mẹta akọkọ ninu wọn ti kú.
Agbenusọ fun ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Kwara, Ọgbẹni Ajayi Okasanmi sọ pe oun ko gbọ nipa iṣẹlẹ naa, àmọ́ oṣiṣẹ kan ni ajọ to n mojuto ọrọ aarun, Alhaji Muhammad Abdullahi fidi iṣẹlẹ naa mulẹ.
O ni awọn meji tó kù naa si ti kuro nileewosan.
"Baba awọn ọmọ naa, to jẹ agbẹ sọ fun wa pe oun ni oun gbin ẹ̀gẹ́ ti wọn fi ṣe elubọ, ti oun ko si le sọ nkan to mu ko fa wahala naa.
- Ó kéré tán, ajínigbé ti pa èèyàn 222 láàrìn oṣù mẹ́ta ní Kaduna- Gomina El Rufai
- Ìjọba Gombe kọ́ iléẹ̀kọ́ tuntun sí ẹgbẹ́ àwọn iléeṣẹ́ elétò aàbò kí ọwọ́ ajínigbé má tẹ̀ akẹ́kọ̀ọ́ mọ́
- Kò sọ́jà mọ́! A ti ti Ọjà Ladipo pa nítorí rògbòdìyàn tó bẹ́ sílẹ̀ níbẹ̀ - `ijọba ìpínlẹ̀ Eko
- Wọ́n ní Ìyá Esabod yẹn ma ń ṣépè, fi òṣèré wọ́lẹ̀, mò ń retí èsì yín sí ọ̀rọ̀ tí mo fi síta yìí - Mr Portable
- Oríire ńlá ló jẹ́ fún àwọn ọmọ Naijiria pé orílẹ̀-èdè yìí ṣì wà ní ọ̀kan ṣoṣo- Buhari
- Sunday Igboho, Akintoye àtàwọn míràn fa Buhari, Malami àtàwọn míì lọ síwájú ilé ẹjọ́ àgbáyé ICC





















