Lukuluku Bantashi: Aláwàdà tí yóò kun èédú sójú, wọ aṣọ ìyá kò bá bàbá tan, ìdúró rẹ̀ lásán pa ní lẹ́rìn-ín

Lukuluku Bantashi

Oríṣun àwòrán, Screen Shot

Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ òde òní, ó ṣeéṣe kí wọ́n má mọ̀ nípa Lukuluku Bantashi.

Sùgbọ́n gbogbo àwọn tó bá ti tó ojú bọ́ láàárín ọdún 1980 sí ọdún 1990, gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú tí orúkọ rẹ̀ kò le parẹ́ ni Lukuluku Bantashi.

Gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú tó lórúkọ lágbolé tíátà, tó sì lo ìgbà tiẹ ní Lukuluku Bantashi ń ṣe nítorí ó ní àmì ìdánimọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò tii lé bá títí di àsìkò yìí.

Fún gbogbo àwọn tó bá wo eré sinimá Yemi My Lover, Ti Oluwa Nilẹ̀, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, máa gbà wí pé láì sí gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú Lukuluku Bantashi nínú àwọn eré láyé ìgbà náà, eré náà kò le tà.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ọ̀kan lára àwọn òṣèré tí ikú kò jẹ́ kí ènìyàn gbádùn obì wọn tó gbó ní Lukuluku Bantashi .

Awo Erin, gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ṣe máa ń pè é, ni ikú ja gbà mọ awọn ololufẹ rẹ lọwọ lásìkò tí àwọn ènìyàn ń gbádùn rẹ̀ jùlọ.

A kò mọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan nípa ìtàn ìgbésí ayé rẹ̀ lẹ́yìn agbo tiata ṣùgbọ́n tí a bá ń sọ̀rọ̀ nípa ká ṣe àwàdà, òdú ni Lukuluku Bantashi, tí kìí ṣe àìmọ̀ fún olóko lẹ́kùn ìwọ̀ oòrùn ilẹ́ Nàìjíríà.

Àkọlé fídíò, Babatunde Adejumo: Ọdún méje ní mi fi sá kúrò nídìí iṣẹ́ aṣerunlọ́sọ̀ọ́ àmọ́ mo padà

Lukuluku Bantashi gẹ́gẹ́ bí aláwàdà:

Nígbà tí Lukuluku Bantashi ń ṣe àwàdà lágbolé tíátà, gbogbo àwọn Baba Suwe, Ajirebi, Godogbo, James Dẹpẹ, Dejo Tunfulu, Larondo àti àwọn mìíràn máa ń tò lẹ́yìn rẹ̀ ni.

Lásìkò yìí, gbogbo àwọn olóòtú eré sinimá ló máa ń fẹ́ kí ó wà nínú àwọn sinimá àwọn nítorí àwòràn rẹ̀ lásán lára pálí ìpolówó, máa ń jẹ́ kí eré bẹ́ẹ̀ tà wàràwàrà.

Bí ó ṣe máa ń gbé ẹnu ẹkún rẹ̀ jẹ́ ohun kan pàtàkì tó yà á sọ́tọ̀ nínú àwọn eléré àti àwọn adẹ́rìnínpòṣónú tí wọ́n jọ lògbà nigba naa.

Àgbàlagbà tí yóò kun èédú sójú, tí yóò wọ aṣọ ìyá kò bá bàbá tan, ni Lukuluku sábà máa ń ṣe nínú eré.

Ìdúró rẹ̀ lásán le mú ènìyàn máa rẹ́rìn-ín àríntọ̀sára.

Lukuluku ati Baba Sufe

Oríṣun àwòrán, Screen Shot

Lukuluku Bantashi ṣe jáde láyé:

Ilẹ̀ mì tìtì ní gbogbo ẹkùn gúúsù ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà ní ọjọ́ tí wọ́n kéde ikú Lukuluku Bantashi lọ́dún 1995.

Gbogbo ilé iṣẹ́ rédíò àti tẹlifíṣàn ló mọ̀ wí pé akọni lọ lọ́jọ́ tí à ń wí yìí.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn òṣèré tíátà ló gbà lọ́jọ́ náà wí pé ká tó rérin ó digbó, ká tó rẹ́fọ̀n, ó dọ̀dàn, ká tó rí irú Lukuluku Bantashi lágbolé tíátà, ó di gbéré.

Gbogbo ènìyàn ló kọrin arò lẹ́yìn akọni tó lọ bi o tilẹ jẹ pe aisan ranpẹ lo se, to fi jade laye, ko si sẹni to fura pe ọlọjọ lo de.

Nígbà tó ń gbìyànú láti gbé ọkàn àwọn ènìyàn kúrò lórí Lukuluku Bantashi, gbajúgbajà agbóhùnsáfẹ́fẹ́, Alhaji Gboyega Lawal sọ nínú ètò rẹ̀ kan wí pé Lukuluku jí ǹ de.

Alhaji Lawal múra fún Yinka Ayefele láti dàbí Lukuluku Bantashi láti gbe wà sórí ètò ONROSY, tí ó sì mú kí àwọn ènìyàn pọ̀ níbi ètò náà.

Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ nígbà àwọn ènìyàn mọ̀ wí pé Lukuluku kọ́ ló wà lábẹ́ aṣọ.

Ó ti pé ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n báyìí tí Lukuluku Bantashi ti fi ayé sílẹ̀ àmọ́ ipò rẹ̀ kò tán lọ́kàn àwọn tó mọ̀ ọ́ nígbà ayé rẹ̀.

Àkọlé fídíò, Baba Suwe: Aya àkọ́fẹ́ olóògbé ṣàlàyé bí àkókó ìkẹyìn ọkọ́ rẹ̀ ṣe rí