Obasanjo: Kò sí ọ̀dọ̀ tó le fi ògòjí mílíọ̀nù náírà ra fọ́ọ̀mù fáwọn olùdíje sípò Ààrẹ

Tambuwal, Saraki ati Atiku

Oríṣun àwòrán, @atiku

Ààrẹ àná lorílẹ̀ èdè Nàìjíríà, Olusegun Obasanjo ti ṣèkìlọ̀ fún àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti máse dìbò tàbí ṣe àtìlẹyìn fún àwọn olùdíje sípò Ààrẹ to ba n parọ.

Aarẹ tẹ́lẹ̀ ni naijiria naa ni oludije tó bá ti sọ wí pé àwọn ikọ̀ kan tàbí ẹgbẹ́ kan ló ra fọ́ọ̀mù láti díje sípò Ààrẹ fún àwọn n parọ ni.

Obasanjo sọ èyí níbi ètò ayẹyẹ ọjọ́ ìbí Pásítọ̀ Itua Ighodalo tó wáyé nílùú Eko.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ẹ ó rántí wí pé awọn oludije fun ipo aarẹ kan ninu ẹgbẹ oselu PDP, ti kede saaju pe awọn ọdọ kan lo da ogoji miliọnu naira jọ lati ra fọọmu idije sipo aarẹ fun awọn.

Lara wọn ni igbákejì Ààrẹ fun ni saa Obasanjo, eyiun Atiku Abubakar ati gómìnà ìpínlẹ̀ Sokoto, Aminu Tambuwal.

Àkọlé fídíò, Abdulfatai Balogun: N kò ríran àmọ́ oníṣòwò Yoghurt ní mí tó ń fi àwìn sàánú fún oníbàárà

Awọn oludije yoku to tun sọ ọrọ naa ni Ààrẹ àná nílé ìgbìmọ̀ aṣòfin, Bukola Saraki, gómìnà àná ìpínlẹ̀ Anambra Peter Obi àti àwọn mìíràn tíwọ́n ti ra fọ́ọ̀mù láti díje dupò Ààrẹ lọ́dún 2023.

Obasanjọ tó wòye wí pé gbogbo ìpèníjà tó ń bá orílẹ̀ èdè yìí fínra wáyé látọwọ́ àwọn olórí tí kò dára, wa rọ àwọn olùdíje náà láti yé parọ́ mọ fún àwọn ará ìlú wí pé ẹnìkan ló ra fọ́ọ̀mù idije sipo aarẹ fún àwọn.

Ó ní kò sí àwọn ọ̀dọ́ tó le ra fọ́ọ̀mù ogójì mílíọ̀nù náírà gẹ́gẹ́ bí àwọn olùdíje náà ṣe ń sọ.

Bákan náà ló ní ẹni tó bá ra fọ́ọ̀mù, kó jáde síta wí pé òun ra fọ́ọ̀mù, kí wọ́n ye parọ́ wí pé ẹnìkan tàbí àwọn ọ̀dọ́ kan ló ra fọ́ọ̀mù fún àwọn.

Àkọlé fídíò, Omi Adio Robbery: Èèyàn márùn-ún tí kò mọwọ́-mẹsẹ̀ ló kú lásìkò ìdigunjalè PoS l‘Omi Adio